Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóẹ́lì 2:23-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

23. Ǹjẹ́ jẹ́ kí inú yín dùn, ẹ̀yin ọmọ Ṣíónì,ẹ sì yọ̀ nínú Olúwa Ọlọ́run yín,nítorí ó ti fi àkọ́rọ̀ òjò fún yín bí ó ti tọ́,Òun ti mú kí òjò rọ̀ sílẹ̀ fún un yín,àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní oṣù kìn-ín-ní.

24. Àwọn ilẹ̀ ìpàkà yóò kún fún ọkà;àti ọpọ́n wọn nì yóò ṣàn jádepẹ̀lú ọti wáìnì tuntun àti òróró.

25. “Èmi yóò sì mú ọdún wọ̀nyí ti eṣú jẹ run padà fún un yín.Èyí tí eṣú agénijẹ àti eṣú jewéjewéọwọ́ eṣú agénijẹ àti kòkòro ajẹnirun mìíràn ti fi jẹàwọn ogun ńlá mí tí mo rán sí àárin yín.

Ka pipe ipin Jóẹ́lì 2