Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 51:11-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. “Lọ ọfà wa kó mú, mú apata! Olúwa ti ru Ọba Médíà sókè,nítorí pé ète rẹ̀ ni láti pa Bábílónì run. Olúwa yóò gbẹ̀san, àní ẹ̀san fún Tẹ́ḿpìlì rẹ̀.

12. Gbé àsìá sókè sí odi Bábílónì!Ẹ ṣe àwọn ọmọ ogun gírí,ẹ pín àwọn olùsọ́ káàkiri,ẹ ṣètò àwọn tí yóò sápamọ́ Olúwa! Yóò gbé ète rẹ̀ jáde,òfin rẹ̀ sí àwọn ará Bábílónì.

13. Ìwọ tí o gbé lẹ́bàá odò púpọ̀,tí o sì ni ọ̀rọ̀ púpọ̀; ìgbẹ̀yìn rẹ ti dé,àní àsìkò láti ké ọ kúrò!

14. Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra fún ara rẹ̀,Èmi yóò fún ọ ní ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ eṣú,wọn yóò yọ ayọ̀, iṣẹ́gun lórí rẹ.

15. “Ó dá ilẹ̀ nípa agbára rẹ̀,o dá ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀,o sì tẹ́ ọ̀run pẹ̀lú ìmọ̀ rẹ̀.

16. Nígbà tí ará omi ọ̀run hóó mú kí òfùrufú ru sókè láti ìpẹ̀kun ayé.Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò,ó sì mú afẹ́fẹ́ jáde láti ilé ìṣúra rẹ̀.

17. “Olúkúlùkù ènìyàn ni kò lọ́pọlọtí kò sì ní ìmọ̀, olúkùlúkùalágbẹ̀dẹ ni a kó ìtìjú bá nípa òrìṣà rẹ̀.Àwọn ère rẹ jẹ́ ẹ̀tàn wọn kò ní èémí nínú.

18. Wọn kò já mọ́ nkànkan,wọ́n jẹ́ ohun ẹlẹ́yà nígbà tí ìdájọ́ wọnbá dé, wọn ó ṣègbé.

19. Ẹni tí ó jẹ́ ìpín Jákọ́bù kó rí bí ìwọ̀nyí;nítorí òun ni ó dá ohun gbogbo,àti gbogbo àwọn ẹ̀yà ajogún, Olúwa alágbára ni orúkọ rẹ̀.

20. “Ìwọ ni kùmọ̀ ohun èlò ogun mi,ohun èlò ìjà mi, pẹ̀lú rẹ èmi ó fọ́ orílẹ̀ èdè túútúú,èmi ó bà àwọn ilé Ọba jẹ́.

21. Pẹ̀lú rẹ, èmi ó pa ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún pẹ̀lú rẹ̀;èmi ó ba kẹ̀kẹ́ ogun jẹ́ pẹ̀lúèmi ó pa awakọ̀

22. Pẹ̀lú rẹ, mo pa ọkùnrin àti obìnrin,pẹ̀lú rẹ, mo paàgbàlagbà àti ọmọdé,Pẹ̀lú rẹ, mo pa ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin.

23. Pẹ̀lú rẹ, mo pa olùsọ́ àgùntànàti agbo àgùntàn rẹ̀;pẹ̀lú rẹ, mo pa àgbẹ̀ àti màlúù,Pẹ̀lú rẹ, mo pa gómìnà àti àwọn alákòóṣo ìjọba rẹ̀.

24. “Ní ojú rẹ, èmi yóò san án fún Bábílónì àti gbogbo àwọn olùgbé inú rẹ̀ fún gbogbo ibi tí wọ́n ti ṣe ní Síónì,”ni Olúwa wí.

25. “Mo lòdì sí ọ, ìwọ òkè apanirunìwọ ti ba gbogbo ayé jẹ́,”ni Olúwa wí.“Èmi ó na ọwọ́ mi sí ọ,èmi yóò yí ọ kúrò lórí àpáta,Èmi yóò sọ ọ́ dàbí òkè tí a ti jó.

26. A kò ní mú òkúta kankan látiọ̀dọ̀ rẹ̀ lò gẹ́gẹ́ bí igun ilé tàbífún ìpínlẹ̀ nítorí pé ìwọ yóò diahoro títí ayé,”ní Olúwa wí.

27. “Gbé àṣíá sókè ní ilẹ̀ náà, fọnipe láàrin àwọn orílẹ̀ èdè!Pèṣè àwọn orílẹ̀ èdè sílẹ̀ láti bá jagun,pe àwọn ìjọba yìí láti doju kọ ọ́,Árárátì, Mínínì àti Ásíkẹ́nì.Yan olùdarí ogun láti kọlù ú,rán àwọn ẹṣin síi bí ọ̀pọ̀ eṣú.

28. Pèsè àwọn orílẹ̀ èdè láti bá jagun,àwọn Ọba Médíà, Gómìnà àti gbogboọmọ ìgbìmọ̀ wọn àti gbogbo orílẹ̀ èdè tí wọ́n jọba lé lórí.

Ka pipe ipin Jeremáyà 51