Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 50:13-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Nítorí ìbínú Olúwa, kì yóò ní olùgbé;ẹnikẹ́ni kò sì ní gbé inú rẹ̀.Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá ni Bábílónì yóòfi ṣe yẹ̀yẹ́ nítorí ọgbẹ́ rẹ̀.

14. “Dúró sí àyè rẹ ìwọ Bábílónìàti gbogbo ẹ̀yin tí ẹ ta ọfà náà.Ẹ ta ọfà náà síi, nítorí ó ti sẹ̀ sí Olúwa.

15. Kígbe mọ-ọn ní gbogbo ọ̀nà!Ó tẹríba, òpó rẹ̀ sì yẹ̀,níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ wí pé èyí ni ìgbẹ̀san Olúwa,gbẹ̀san lára rẹ̀.Ṣe síi gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí àwọn ẹlòmìíràn.

16. Mú kúrò ní Bábílónì olùgbìnàti olùkórè pẹ̀lú ohun ìkórè rẹ̀.Nítorí idà àwọn aninilárajẹ́ kí oníkálùkù padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀,kí oníkálukú sì sá padà sí ilẹ̀ rẹ̀.

17. “A ti fọ́n Ísírẹ́lì ká, Kìnnìún sì ti lé e lọ.Ẹni àkọ́kọ́ tí ó kọ́kọ́ jẹ ẹ́ ni Ọba Ásíríà,ẹni tí ó sì jẹ eegun rẹ̀kẹ́yìn ni Nebukadinésárì Ọba Bábílónì.”

18. Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run alágbára Ọlọ́run Ísírẹ́lì wí;“Ǹ ó fi ìyà jẹ Ọba Bábílónì àti ilẹ̀ rẹ̀gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe fìyà jẹ Ọba, Ásíríà.

19. Ṣùgbọ́n, èmi yóò mú Ísírẹ́lìpadà wá pápá oko tútù rẹ̀òun yóò sì máa bọ́ ara rẹ̀ lórí kámẹ̀lì àti Básánì,a ó sì tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn ní òkèÉfúráímù àti ní Gílíádì

20. Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,”ni Olúwa wí,“À ó wá àìṣedéédé ẹ̀ṣẹ̀ Ísírẹ́lì,ṣùgbọ́n a ki yóò rí ìkankan;àti ẹṣẹ Júdà a ki yóò sì rí wọnnítorí èmi yóò dáríjìn àwọn tí ó ṣẹ́kù tí mo dásí.

21. “Kọlu ilẹ̀ Mérátamù àti àwọntí ó ń gbé ní Pékódì.Kọlùú pa á, kí o sì párun pátapáta,”ni Olúwa wí“Ṣe gbogbo ohun tí mo paláṣẹ fún ọ.

22. Ariwo ogun wà ní ilẹ̀ náàìrọ́kẹ̀rẹ̀ ìparun ńlá.

23. Wo bi ilé ayé ti pín sí wẹ́lẹ́wẹ́lẹ́ tó.Wo bí Bábílónì ti di aláìlólùgbéni àárin àwọn orílẹ̀ èdè.

24. Mo dẹ pàkúté sílẹ̀fún ọ ìwọ Bábílónì,kí o sì tó mọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀,o ti kó sínú rẹ̀. A mú ọ nítorí pé o tako Olúwa.

25. Olúwa ti kó àwọn ohun èlòìjà rẹ̀ jáde, nítorí pé OlúwaỌlọ́run ọmọ ogun ti ṣiṣẹ́ ní ilẹ̀ Bábílónì.

26. Ẹ dìde sí láti ilẹ̀ jínjínpárun pátapáta láìṣẹ́kù.

Ka pipe ipin Jeremáyà 50