Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 49:2-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà ń bọ̀,”ni Olúwa wí;“nígbà tí èmi yóò mú ìdágìrì ogun bá Rábàtí Ámónì yóò sì di òkítì ahoro,gbogbo ìlú tí ó yí i ká ni a ó jó níná.Nígbà náà ni Ísírẹ́lì yóòlé wọn, àwọn tí ó ti lé e jáde,”ni Olúwa wí.

3. “Pohùnréré ẹkún ìwọ Hésíbónìnítorí Áì tí rún, kígbe jádeẹ̀yin ènìyàn Rábà, ẹ wọ aṣọọ̀fọ̀ kí ẹ sì ṣọ̀fọ̀. Ẹ sárésókè sódò nínú ọgbà nítoríMákómù yóò lọ sí ìgbèkùnpẹ̀lú àwọn àlùfáà àti ìjòyè rẹ̀.

4. Kí ló dé tí ẹ fi ń fi àfonífojì yín yangàn?Ẹ fi àfonífojì yín yangàn pẹ̀lú èṣo rere,ẹ̀yin ọmọbìnrin aláìsòótọ́.Gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ yín, ẹ sì wí pé,‘ta ni yóò kò mí lójú?’

5. Èmi yóò mu ẹ̀rù wá lórí rẹláti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tó yí ọ ká,”ni Olúwa wí:

6. “Olúwa àwọn ọmọ ogun.Gbogbo yín ni ó lé jáde, kò sì sí ẹnìkantí yóò dá ìkólọ Ámónì padà,”ni Olúwa wí.

7. Nípa Édómù:Èyí ní ohun tí Olúwa àwọn ọmọ ogun wí:“Ṣe kò ha sí ọgbọ́n mọ́ ni Temánì?Ṣé a ti ké ìmọ̀ràn kúrò ní ọ̀dọ̀ olóyè?Ṣé ọgbọ́n wọn ti bàjẹ́ bí?

8. Yípadà kí o sálọ, sá pamọ́ sínú ihò,ìwọ tí ó ń gbé níDédánì nítorí èmi yóò múibi wá sórí Ísọ̀ ní àkókò tí èmi ó fìyà jẹ́ẹ́.

9. Tí àwọn tí ń ṣa èso bá tọ̀ ọ́ wá;ǹjẹ́ wọn kò ní fi èso díẹ̀ sílẹ̀?Tí olè bá wá ní òru; ǹjẹ́ wọn kò níkó gbogbo ohun tí wọ́n bá fẹ́?

10. Ṣùgbọ́n èmi yóò tu Ísọ̀ sí ìhòòhòèmi kò ní bo ibi ìkọ̀kọ rẹnítorí kí o máa baà fi ara rẹ pamọ́.Àwọn ọmọ rẹ, ẹbí rẹ àtiàwọn ará ilé rẹ yóò parun.Wọn kò sì ní sí mọ́.

11. Fi àwọn ọmọ aláìní baba sílẹ̀èmi yóò dábòbo ẹ̀mí wọn.Àwọn opó rẹ gan an lè gbékẹ̀lẹ́ mi.”

12. Èyí ni ohun tí Olúwa wí bí ẹnikẹ́ni tí kò bá yẹ kí ó mu ife náà bá mú un, kí ló dé tí ìwọ yóò fi lọ láìjìyà? Ìwọ kò ní lọ láìjìyà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò mu un.

Ka pipe ipin Jeremáyà 49