Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 49:14-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Èmi ti gbọ́ ọ̀rọ̀ kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa:A rán ikọ̀ kan sí orílẹ̀ èdè láti sọ.Ẹ kó ara yín jọ láti dojúkọ ọ́, ẹ dìde fún ogun.

15. “Ní báyìí, èmi yóò sọ ọ́ dikékeré láàrin orílẹ̀ èdè gbogbo;ẹni ẹ̀gàn láàrin àwọn ènìyàn.

16. Ìpayà tí ìwọ ti fà sínúìgbéraga ọkàn rẹ sì ti tàn ọ́ jẹ;ìwọ tí ń gbé ní pàlàpáláàpáta tí o jòkó lórí ìtẹ́ gígasíbẹ̀ o kọ́ ìtẹ́ rẹ ga gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ idì;láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá,”ni Olúwa wí.

17. “Édómù yóò di ahorogbogbo àwọn tí ń kọjá yóò jáyà, wọn ó sìfi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà nítorí gbogbo ìpalára rẹ

18. Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe gba Sódómùàti Gòmórà pẹ̀lú àwọn ìlútí ó wà ní àyíká rẹ,”ní Olúwa wí.“Bẹ́ẹ̀ ni, kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé níbẹ̀;kò sì ní sí ènìyàn tí yóò tẹ̀dó síbẹ̀ mọ́.

19. “Bí kìnnìún ti ń bọ̀ láti igbóJódánì wá sí pápá oko ọlọ́rà áèmi yóò lé Édómù láti ibi ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá.Ta ni ẹni náà tí èmi yóò yàn fún èyí?Ta lo dàbí èmi, ta ni ó le pè mí níjà?Ta ni olùsọ́ àgùntàn náà tí ó lè dúró níwájú mi?”

20. Nítorí náà, ẹ gbọ́ ohun tí Olúwa ní fún Édómù, ohun tíó ní ní pàtàkì fún àwọn tí ń gbé ní Témánì.Àwọn ọ̀dọ́ àgbò ni à ó lé jáde.Pápá oko wọn ni yóò run nítorí wọn.

21. Nípa ìṣubú ariwo wọn, ilẹ̀yóò mì, a ó gbọ́ igbe wọnní òkun pupa.

Ka pipe ipin Jeremáyà 49