Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 38:4-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Nígbà náà ni àwọn ìjòyè wí fún Ọba pé, “Ó yẹ kí a pa ọkùnrin yìí; ó ń kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ ogun tó kù nínú ìlú pẹ̀lú gbogbo àwọn ènìyàn nípa ohun tí ó ń sọ fún wọn. Ọkùnrin yìí kò fẹ́ ire fún àwọn ènìyàn bí kò ṣe ìparun.”

5. Sedekáyà Ọba sì wí pé, “Ó wà lọ́wọ́ yín. Ọba kò lè ṣe ohunkóhunm láti ta kò yín.”

6. Wọ́n gbé Jeremáyà sọ sínú àmù Málíkíà ọmọ Ọbakùnrin tó wà ní àgbàlá àwọn ẹ̀ṣọ́, wọ́n ju Jeremáyà sínú àmù pẹ̀lú okùn; kò sì sí omi níbẹ̀ àyàfi ẹrọ̀fọ̀ nìkan, Jeremáyà sì rì sínú ẹrọ̀fọ̀.

7. Ṣùgbọ́n, Ebedimélékì, ará Kúṣì ìjòyè nínú ààfin Ọba gbọ́ pé wọ́n ti ju Jeremáyà sínú àmù. Nígbà tí Ọba jókòó lẹ́nubodè Bẹ́ńjámínì.

8. Ebedimélékì jáde kúrò láàfin ó sì sọ fún un pé,

9. “Olúwa mi Ọba, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ti ṣe ohun búburú sí Jeremáyà òjíṣẹ́ Ọlọ́run. Wọ́n ti gbé e sọ sínú àmù níbi tí kò sí oúnjẹ kankan nínú ìlú mọ́.”

10. Nígbà náà ni Ọba pàṣẹ fún Ebedimélékì ará Kúṣì pé, “Mú ọgbọ̀n ọkùnrin láti ibí pẹ̀lú rẹ, kí ẹ sì lọ yọ Jeremáyà òjíṣẹ́ Ọlọ́run kúrò nínú àmù kí ó tó kú.”

11. Ebedimélékì kó àwọn ọkùnrin náà pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n lọ sínú yàrá kan nínú ààfin Ọba. Ó mú àwọn aṣọ àkísà àti okùn tọ Jeremáyà lọ nínú àmù.

12. Ebedimélékì sọ fún Jeremáyà pé, “Fi àkísà àti okùn bọ abẹ́ abíyá rẹ, Jeremáyà sì ṣe bẹ́ẹ̀.”

13. Báyìí ni wọ́n ṣe yọ ọ́ jáde, ó sì ń gbé àgbàlá àwọn ẹ̀ṣọ́.

14. Nígbà náà ni Ọba Sedekáyà ránṣẹ́ pe, Jeremáyà òjíṣẹ́ Ọlọ́run àti láti mú un wá sí ẹnubodè kẹta nílé Ọlọ́run. Ọba sì sọ fún Jeremáyà pé, “Èmi yóò bi ọ́ ní ohun kan; má sì ṣe fi ohun kan pamọ́ fún mi.”

15. Jeremáyà sì sọ fún Sedekáyà pé, “Tí mo bá fún ọ ní èsì, ṣé o kò ní pa mí? Tí mo bá gbà ọ́ nímọ̀ràn, o kò ní gbọ́ tèmi.”

Ka pipe ipin Jeremáyà 38