Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 38:23-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

23. “Wọn yóò kó àwọn ìyàwó àti ọmọ rẹ wá sí Bábílónì. Ìwọ gan-an kò ní bọ́ níbẹ̀, Ọba Bábílónì yóò mú ọ, wọn yóò sì jó ìlú yìí kanlẹ̀.”

24. Nígbà náà ni Sedekáyà sọ fún Jeremáyà pé, “Má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni mọ̀ nípa ọ̀rọ̀ yìí, tàbí kí o kú.

25. Tí àwọn ìjòyè bá mọ̀ pé mo bá ọ sọ̀rọ̀, tí wọ́n bá wá bá ọ wí pé, ‘Sọ fún wa ohun tí o bá Ọba sọ tàbí ohun tí Ọba sọ fún ọ; má ṣe fi pamọ́ fún wa tàbí kí a pa ọ́,’

26. nígbà náà kí o sọ fún wọn, ‘Mò ń bẹ Ọba láti má jẹ́ kí n padà lọ sí ilé Jónátanì láti lọ kú síbẹ̀.’ ”

27. Gbogbo àwọn olóyè sì wá sí ọ̀dọ̀ Jeremáyà láti bi í léèrè, ó sì sọ gbogbo ohun tí Ọba ní kí ó sọ. Wọn kò sì sọ ohunkóhun mọ́, nítorí kò sí ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ tí òun àti Ọba jọ sọ.

28. Jeremáyà wà nínú àgbàlá àwọn ẹ̀ṣọ́ títí di ọjọ́ tí wọ́n fi kó Jérúsálẹ́mù

Ka pipe ipin Jeremáyà 38