Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 36:15-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Wọ́n sì wí fún pé, “Jòkòó, jọ̀wọ́ kà á sí etí wa!”Nígbà náà ni Bárúkì sì kàá ní etí wọn.

16. Nígbà tí wọ́n sì gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ náà tan; wọ́n ń wo ara wọn lójú pẹ̀lú ẹ̀rù. Wọ́n sì wí fún Bárúkì pé, “Àwa gbọdọ̀ jábọ̀ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún Ọba.”

17. Wọ́n sì bèèrè lọ́wọ́ Bárúkì pé, “Sọ fún wa báwo ni o ṣe kọ gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí? Ṣé Jeremáyà ló sọ wọ́n?”

18. Bárúkì sì dá wọn lóhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, láti ẹnu rẹ̀ ni, ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ báyìí fún mi, èmi sì fi tàdáwà kọ wọ́n sínú ìwé náà.”

19. Nígbà náà ni àwọn ìjòyè sọ fún Bárúkì wí pé, “Lọ fi ara rẹ pamọ́ àti Jeremáyà, má sì ṣe jẹ́ kí ẹnìkan mọ ibi tí ẹ̀yin wà.”

20. Lẹ́yìn tí wọ́n fi ìwé kíkà náà pamọ́ sí iyàrá Elisámà akọ̀wé, wọ́n sì wọlé tọ Ọba lọ nínú àgbàlá, wọ́n sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ náà ní etí Ọba.

21. Ọba sì rán Jéhúdù láti lọ mú ìwé kíká náà wá láti inú iyàrá Elisámà akọ̀wé. Ó sì ka ìwé náà ní etí Ọba àti ní etí gbogbo àwọn ìjòyè tí ó dúró ti Ọba.

Ka pipe ipin Jeremáyà 36