Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 27:19-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Nítorí pé, èyí ni ohun tí Olúwa sọ nípa àwọn opó, omi òkun níti ìpilẹ̀ṣẹ̀ àti níti ohun èlò ìyókù tí ó kù ní orílẹ̀ èdè náà.

20. Èyí tí Nebukadinésárì Ọba Bábílónì kò kó lọ nígbà tí ó mú Jéhóíákímù Ọba Júdà lọ sí ìgbèkùn láti Jérúsálẹ̀mù lọ sí Bábílónì, pẹ̀lú àwọn ọlọ́lá Júdà àti Jérúsálẹ́mù.

21. Lóòótọ́, èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Ísírẹ́lì wí nípa àwọn ohun ìṣúra tí ó ṣẹ́kù ní ilé Olúwa àti ní ààfin Ọba Júdà àti ní Jérúsálẹ́mù:

22. ‘A ó mú wọn lọ sí ilẹ̀ Bábílónì, ní ibẹ̀ ni wọn ó sì wà títí di ìgbà tí mo bá padà,’ èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa. ‘Lẹ́yìn èyí, mà á mú wọn padà, Èmi yóò sì ṣe wọ́n lọ́jọ̀ ní ibí yìí.’ ”

Ka pipe ipin Jeremáyà 27