Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 23:36-40 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

36. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọdọ̀ dárúkọ ọ̀rọ̀ ‘ìjìnlẹ̀ Olúwa’ mọ́, nítorí pé ọ̀rọ̀ oníkálùkù ènìyàn di ọ̀rọ̀ ìjìnlẹ̀ rẹ̀. Nítorí náà, ẹ̀yin ń yí ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run alágbára alààyè padà.

37. Èyí ni ohun tí ẹ̀yin ń sọ fún wòlíì: ‘Kí ni ìdáhùn Olúwa sí ọ́?’ tàbí ‘Kí ni ohun tí Olúwa bá ọ sọ?’

38. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀yin ń sọ wí pé, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀ ìjìnlẹ̀ Olúwa,’ èyí ni ohun tí Olúwa sọ: Ó ń lo ọ̀rọ̀ yìí, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀ ìjìnlẹ̀ Olúwa,’ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo sọ fún un yín láti má ṣe gbà á, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀ ìjìnlẹ̀ Olúwa.’

39. Nítorí náà, Èmi yóò gbàgbé yín, bẹ́ẹ̀ ni n ó lé e yín kúrò níwájú mi pẹ̀lú àwọn orílẹ̀ èdè tí mo fi fún un yín àti àwọn baba yín.

40. Èmi yóò sì mú ìtìjú ayérayé wá sí orí yín, ìtìjú tí kò ní ní ìgbàgbé.”

Ka pipe ipin Jeremáyà 23