Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 22:7-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Èmi ó rán apanirun sí ọolúkúlùkù ọkùnrin pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀,wọn yóò sì gé àsànyàn igi kédárì rẹ lulẹ̀,wọn ó sì kó wọn jù sínú iná.

8. “Àwọn ènìyàn láti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀ èdè yóò rékọjá lẹ́bàá ìlú yìí wọn yóò sì máa bi ara wọn léèrè pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe irú èyí sí ìlú ńlá yìí?’

9. Ìdáhùn wọn yóò sì jẹ́: ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, wọn ti ń fi oríbalẹ̀ fún Ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì sìn wọ́n.’ ”

10. Nítorí náà má ṣe sunkún nítorí Ọba tí ó ti kú tàbí sọ̀fọ̀ fún àdánù rẹ̀,ṣùgbọ́n ẹ sunkún kíkorò fún ẹni tí a lé kúrò nílùúnítorí kì yóò padà wá mọ́tàbí fi ojú rí ilẹ̀ tí a ti bí i.

11. Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa Ṣálúmù ọmọ Jòsáyà Ọba Júdà tí ó jọba lẹ́yìn baba rẹ̀, ṣùgbọ́n tí ó jáde kúrò níhìn ín: “Òun kì yóò padà wá mọ́.

12. Yóò kú ni ibi tí a mú u ní ìgbèkùn lọ, kì yóò sì rí ilẹ̀ yìí mọ́.”

13. “Ègbé ni fún ẹni tí a kọ́ ààfin rẹ̀ lọ́nà àìsòdodo,àti àwọn yàrá òkè rẹ̀ lọ́nà àìtọ́tí ó mú kí àwọn ará ìlú rẹ ṣiṣẹ́ lásánláì san owó iṣẹ́ wọn fún wọn.

14. Ó wí pé, ‘Èmi ó kọ́ ààfin ńlá fún ara miàwọn yàrá òkè tí ó fẹ̀,ojú fèrèsé rẹ̀ yóò tóbi.’A ó sì fi igi kédárì bò ó,a ó fi ohun aláwọ̀ pupa ṣe é ní ọ̀ṣọ́.

15. “Nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ igi kédárì, a sọ ọ́ di Ọbababa rẹ kò ha ní ohun jíjẹ àti mímu?Ó ṣe ohun tí ó tọ́ ni ó fi dára fún un.

16. Ó gbéjà òtòsì àti aláìní,ohun gbogbo sì dára fún un.Ìyẹn ha kọ́ ni mímọ́ mi túmọ̀ sí?”ni Olúwa wí.

17. “Ṣùgbọ́n ojú àti ọkàn rẹwà lára rẹ̀ ní èrè àìsòtítọ́láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ìnilára àti ìlọ́nilọ́wọ́gbà.”

18. Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, nípa Jehóíákímù ọmọ Jòsáyà, Ọba Júdà:“Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un:wí pé, ‘Ó ṣe, arákùnrin mi! Ó ṣe, arábìnrin mi!’Wọn kì yóò sọ̀fọ̀ fún un:wí pé, ‘Ó ṣe, olúwa tàbí ó ṣe kábíyèsí!’

19. A ó sin òkú rẹ̀ bí i kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́tí a wọ́ sọnù gba ti ẹnubodèJérúsálẹ́mù.”

20. “Gòkè lọ sí Lẹ́bánónì, kígbe sítakí a sì gbọ́ ohùn rẹ ní Básánì,kí o kígbe sókè láti Ábárímù,nítorí a ti run gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ túútúú.

Ka pipe ipin Jeremáyà 22