1. Èyí ní ohun tí Olúwa wí: “Lọ ra ìkòkò lọ́dọ̀ alámọ̀, mú dání lára àwọn àgbààgbà ọkùnrin àti wòlíì.
2. Hó sí àfonífojì Bẹni Hínínónì, nítòsí ẹnu ọ̀nà àbáwọlé pótísẹ́dì níbẹ̀ sì ni kí o kéde ọ̀rọ̀ tí mo bá ọ sọ.
3. Kí o sì wí pé ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin Ọba àwọn Júdà àti ẹ̀yin ará Jérúsálẹ́mù. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Ísírẹ́lì sọ. Dẹtí sí mi! Èmi yóò mú ìparun wá síbí, etí gbogbo wọn tó bá gbọ́ ọ yóò hó yaya.
4. Nítorí wọ́n ti gbàgbé mi, wọ́n sì ti sọ ibí di ilé fún òrìṣà àjòjì; wọ́n ti sun ẹbọ nínú rẹ̀ fún òrìṣà tí àwọn baba wọn tàbí tí Ọba Júdà kò mọ̀ rí, wọ́n ti fi ẹ̀jẹ̀ aláìsẹ̀ kún ilẹ̀ yìí.