12. Ṣùgbọ́n wọn yóò sọ wí pé, ‘Kò se nǹkànkan, àwa yóò tẹ̀ṣíwájú nínú èrò wa, ẹnìkọ̀ọkan wa, yóò tẹ̀lé agídí ọkàn búburú rẹ̀.’ ”
13. Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí:“Ẹ bèèrè nínú orílẹ̀ èdè, ẹni tíó bá ti gbọ́ irú nǹkan wọ̀nyí ri?Ohun tí ó burú gidi ni wúndíá Ísírẹ́lì ti ṣe.
14. Ǹjẹ́ omi ojo rírí Lébánónì yóò diàwátì láti ibi àpáta? Sí omi tútùtí ó jìnnà sí orísun rẹ yóò kọ̀ láti ṣàn bí?
15. Síbẹ̀ ni àwọn ènìyàn mi ti gbàgbé mi,wọ́n sun tùràrí fún òrìṣà aṣántí ó mú wọn kọsẹ̀ ní ọ̀nà wọn àti ọ̀nà wọn àtijọ́.Wọ́n mú wọn rìn ní ọ̀nà àtijọ́ àti ní ojú tí a kò kọ́
16. Ilẹ̀ wọn yóò wà lásán yóò sì dinǹkan ẹ̀gàn títí láé. Gbogboàwọn tí ó ń kọjá yóò bẹ̀rù, wọnyóò sì mi orí wọn.
17. Gẹ́gẹ́ bí afẹ́fẹ́ láti ìlà oorùn,Èmi yóò tú wọn ká lójú àwọn ọ̀tá wọn.Èmi yóò sì kọ ẹ̀yìn sí wọn, n kì yóò kọjú sí wọnní ọjọ́ àjálù wọn.”
18. Wọ́n sọ wí pé, “Wá, jẹ́ kí a lọ ṣọ̀tẹ̀ sí Jeremáyà, nítorí òfin ikọ́ni láti ẹnu àwọn àlùfáà kì yóò já sí asán, tàbí ìmọ̀ràn fún àwọn ọlọ́gbọ́n tàbí ọ̀rọ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì. Nítorí náà wá, ẹ jẹ́ kí a kọlùú pẹ̀lú ahọ́n wa, kí a má sì ṣe tẹ́tí sí ohun kóhun tí ó bá sọ.”