Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 17:13-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Olúwa olùgbẹ́kẹ̀lé Ísírẹ́lìgbogbo àwọn tí ó kọ̀ ọ́ sílẹ̀ niojú ó tì: gbogbo àwọn tí ó padàṣẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ ni a ọ́ kọorúkọ wọn sínú ekuru, nítorí wọ́nti kọ Olúwa orísun omi ìyè wọn sílẹ̀.

14. Wò mí sàn Olúwa, èmi yóò diẹni ìwòsàn, gbà mí là, èmi yóòdi ẹni ìgbàlà, nítorí ìwọ ni ìyìn mi.

15. Wọ́n sọ fún mi wí pé:“Níbo ni ọ̀rọ̀ Olúwa wà?Jẹ́ kí ó di ìmúsẹ báyìí.”Ni Olúwa wí.

16. Èmi kò sá kúrò láti máa jẹ́ olùsọàgùntàn rẹ, ìwọ mọ̀ wí pé èmikò kẹ̀rẹ̀ ní ọjọ́ ìpọ́njú. Ohun tíó jáde ní ètè mi jẹ́ èyí tí ó hàn sí ọ.

17. Má ṣe di ìbẹ̀rù fún mi, ìwọ niààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú

18. Jẹ́ kí ojú ti àwọn ẹni tí ń lépa mi,ṣùgbọ́n pa mí mọ́ kúrò nínúìtìjú, jẹ́ kí wọn ó bẹ̀rù. Múọjọ́ ibi wá sórí wọn, fi ìparunìlọ́po méjì pa wọ́n run.

19. Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún mi: “Lọ dúró ní ẹnu ọ̀nà àwọn ènìyàn níbi tí àwọn Ọba Júdà ń gbà wọlé tí wọ́n ń gbà jáde àti ní gbogbo ẹnu bodè Jérúsálẹ́mù.

20. Sọ fún wọ́n pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin Ọba Júdà àti gbogbo ẹ̀yin ènìyàn Júdà àti gbogbo ẹ̀yin tí ń gbé ní Jérúsálẹ́mù tí ń wọlé láti ẹnu-bodè yìí.

21. Báyìí ni Olúwa wí ẹ kíyèsi láti máa ru ẹrù lọ́jọ́ ìsinmi tàbí kí ẹ gbé wọlé láti ẹnu-bodè Jérúsálẹ́mù.

22. Má ṣe gbé ẹrù jáde kúrò nínú ilé yín, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe ṣe isẹ́kísẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ṣùgbọ́n kí ẹ pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ fún àwọn baba ńlá yín.

23. Ṣíbẹ̀ wọn kò gbọ́ tàbí tẹ́tí sílẹ̀, wọ́n jẹ́ Ọlọ́rùn líle; wọn kì í fẹ́ gbọ́ tàbí gba ìbáwí.

24. Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá kíyèsí láti gbọ́ tèmi ní Olúwa wí, tí ẹ kò sì gbe ẹrù gba ti ẹnu bodè ìlú ní ọjọ́ ìsinmi, ṣùgbọ́n tí ẹ ya ọjọ́ ìsinmi, sí mímọ́, nípa pé ẹ kò ṣe iṣẹ́kísẹ́ ní ọjọ́ náà.

Ka pipe ipin Jeremáyà 17