Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 5:15-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. O ó wá di ẹ̀gàn, ẹ̀sín àti ikílọ àti ohun ẹ̀rù àti ìyanu fún àwọn orílẹ̀ èdè tó yí ọ ká nígbà tí mo bá fìyà jẹ ọ́ nínú ìbínú àti nínú ìbínú gbígbóná mi. Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀.

16. Nígbà tí mo bá ta ọfà ikú àti ìparun pẹ̀lú ìyàn, n ó ta á láti run ọ́ ni. N ó gé ìpèsè oúnjẹ kúrò, n ó sì mú ìyàn wá lọ́pọ̀lọpọ̀.

17. Èmi yóò rán ìyàn àti ẹranko búburú sí i yín, wọn yóò fi yín sílẹ ni àìlọ́mọ. Àjàkálẹ̀ àrùn àti ìtàjẹ̀-sílẹ̀ yóò kọjá láàrin yín. Èmi yóò si mú idà wá sórí rẹ. Èmi Olúwa ló sọ bẹ́ẹ̀.”

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 5