Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 40:14-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Ó wọ̀n ọ́n lọ sí àwọn ojú àwọn ìgbéró ògiri gbogbo rẹ̀ yí inú òjú ọ̀nà ó jẹ́ ọgọ́ta ìgbọ̀nwọ́. Ìwọ̀n náà tó àtẹ̀wọ́ ẹnu ọ̀nà tí ó dojúkọ àgbàlá.

15. Ìjìnà ẹnu ọ̀nà àbáwọlé títí dé ìparí yàrá kéékèèkéé náà àti àwọn ìgbéró ògiri nínú ẹnu ọ̀nà ní a gbé dá jẹ́ àádọ́ta ìgbọ̀nwọ́.

16. Ni a tẹ nínú yíká; àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta náà ní fèrèsé tóóró tí ó wọ inú yíká; Awọn ògiri wọn ní inú ni a fi pákó tẹ yíká láti ilẹ̀ dé òkè fèrèsé ati láti fèrèsé dé òrùlé.

17. Lẹ́yìn náà ó mú mi lọ sí ojú òde àgbàlá. Níbẹ̀ mo rí yàrá díẹ̀ àti pèpéle tí a kọ́ yí àgbàlá ká; ọgbọ̀n yàrá wà lẹ́gbẹ̀ pèpéle náà,

18. O ṣe ààlà sí ẹ̀gbẹ́ àwọn ẹnu ọ̀nà, ìbú rẹ̀ sì jẹ́ bákan náà pẹ̀lú gígun rẹ̀: èyí jẹ́ pèpéle tí ìsàlẹ̀.

19. Lẹ́yìn náà, o wọn jíjìnna rẹ̀ láti inú ìsàlẹ̀ ẹnu ọ̀nà títí dé àgbàlá tí inú; ó jẹ́ ọgọ́rùn-ún ìgbọ̀nwọ́ ni ìhà ìlà òòrùn àti tí àríwá.

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 40