Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 40:1-3 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní ọdún kẹẹdọ́gbọ̀n tí a ti wà ni oko ẹrú wa, ní ìbẹ̀rẹ̀ ọdún, ni oṣù kẹwàá ọdún kẹ́rinlá lẹ́yin ìsubú ìlú ńlá náà ní ọjọ́ náà gan an ọwọ́ Olúwa ń bẹ̀ lára mi, oùn sì mú mi lọ síbẹ̀.

2. Nínú ìran Ọlọ́run, ó mú mí lọ sí ilẹ̀ Ísírẹ́lì, ó sì gbé mi lọ sí orí òkè gíga fíofío. Ní ẹ̀gbẹ́ gúsù ọ̀pọ̀ ilé tó wà níbẹ̀ dàbí ìlú ńlá.

3. Ó mú mi lọ síbẹ̀, mo sì rí ọkùnrin kan tí ìrírí rẹ̀ dàbí ìrí bàba; ó dúró ni ẹnu ọ̀nà pẹ̀lú okùn aṣọ ọ̀gbọ̀ funfun àti ọ̀pá ìwọnlẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀.

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 40