Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 37:10-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Nítorí náà, mo ṣọtẹ́lẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ṣe pa á láṣẹ fún mi, èémí sì wọ inú wọn; Wọ́n di alààyè, wọ́n sì dìde dúró lórí ẹṣẹ̀ wọn—pẹ̀lú ìhámọ́ra tí ó pọ̀.

11. Lẹ́yìn náà ó ṣọ fún mi: “Ọmọ ènìyàn, àwọn egungun wọ̀nyí ni gbogbo ìdílé Ísírẹ́lì. Wọ́n ṣọ wí pé, ‘Egungun wa ti gbẹ ìrètí wa sì ti lọ; a ti gé wa kúrò.’

12. Nítorí náà ṣọtẹ́lẹ̀, kí o sì ṣọ fun wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: Ẹ̀yin ènìyàn mi, Èmi yóò sí àwọn ibojì yín, èmi yóò sì mú yín wá si ilẹ̀ Isírẹ́lì.

13. Ẹ̀yin o sì mọ̀ èmi ni Olúwa, nígbà tí èmi bá ti sí bojì yín, ẹ̀yin ènìyàn mi, ti èmi bá si mú un yín dìde kúrò nińú bojì yín

14. Èmi yóò fi èémí mi sínú yín, ẹ̀yin yóò sì yè, èmi yóò sì mú kí ẹ fi lélẹ̀ ní ilẹ̀ ẹ̀yín tìkára yín. Nígbà náà ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Olúwa ti ṣọ̀rọ̀, èmi sì ti ṣe ni Olúwa wí.’ ”

15. Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mi wá:

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 37