Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 37:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ọwọ́ Olúwa wà lára mi, ó sì mú mi jáde pẹ̀lú ẹ̀mí Olúwa, ó mú kí ń wà ní àárin àfonífojì; ti o kún fún àwọn egungun.

2. Ó mú mi lọ síwájú àti sẹ́yìn láàrin wọn, èmi sì rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn egungun ní orí ilẹ̀ àfonífojì, àwọn egungun tí ó gbẹ gan.

3. Olúwa sì bi mí léèrè, “Ọmọ ènìyàn, ǹjẹ́ àwọn egungun wọ̀nyí lè yípadà di àwọn ènìyàn bí?”Èmi sì wí pé, “Ìwọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ìwọ nìkan ni o lè dáhùn sí ìbéèrè yìí.”

4. Nígbà náà ni ó wí fún mi pé, “Ṣọtẹ́lẹ̀ sí àwọn egungun kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Ẹ̀yin egungun gbígbẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!

5. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí fún àwọn egungun wọ̀nyí: Èmi yóò mú kí èémí wọ inú yín ẹ̀yin yóò sì wá di ààyè.

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 37