Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 32:6-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Ẹ̀jẹ̀ rẹ ti ń ṣàn ní èmi yóò sì fi rin ilẹ̀ náàgbogbo ọ̀nà sí orí àwọn òkè gíga,àwọn àlàfo jínjìn ní wọn yóò kún fún ẹran ara rẹ.

7. Nígbà tí mo bá fọ́n ọ jáde, èmi yóò pa ọ̀run déàwọn ìràwọ̀ wọn yóò sì ṣókùnkùn;èmi yóò sì fi ìkùukùu bo oòrùnòṣùpá kì yóò sì tan ìmọ́lẹ̀ rẹ̀

8. Gbogbo ìmọ́lẹ̀ títàn ní ojú ọ̀runni èmi yóò mú ṣókùnkùn lórí rẹ;èmi yóò mú òkùnkùn wá sórí ilẹ rẹ,ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí

9. Èmi yóò da ọkàn ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn rúnígbà tí mo bá mú ìparun rẹ wání àárin àwọn orílẹ̀ èdè tí ìwọkò í tí ì mọ̀.

10. Èmi yóò mú kí ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn dẹ́rù bà ọ́,àwọn Ọba wọn yóò sì wárìrì fúnìbẹ̀rù pẹ̀lú ìpayà nítorí rẹ,nígbà tí mo bá ju idà mi ní iwájú wọnNí ọjọ́ ìṣubú rẹìkọ̀ọ̀kan nínú wọn yóò wárìrìní gbogbo ìgbà fún ẹ̀mí rẹ.

11. “ ‘Nítorí èyí yìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí:“ ‘Idà Ọba Bábílónìyóò wá sí orí rẹ,

12. Èmi yóò mú kí ìjọ ènìyàn rẹ kí ótí ipa idà àwọn alàgbà ènìyàn ṣubúàwọn orílẹ̀ èdè aláìláàánú jùlọ.Wọn yóò tú ìgbéraga Éjíbítì ká,gbogbo ìjọ rẹ ní a óò dá ojú wọn bolẹ̀.

13. Gbogbo ẹran ọ̀sìn rẹ ni èmi yóòparun ní ẹgbẹ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omikì i ṣe ẹsẹ̀ ènìyàn ní yóò tẹ ibẹ̀ẹsẹ̀ ẹran ọ̀sìn kì yóò sì mú kí ibẹ̀ ni arọ̀fọ̀.

14. Lẹ́yìn náà èmi yóò mú kí omi rẹ̀ tòròkí àwọn odò rẹ̀ kí o ṣàn bí epo,ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 32