Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 18:1-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:

2. “Kín ni ẹ̀yín rò tí ẹ̀yin fi ń pa òwe nípa Ísírẹ́lì wí pé:“ ‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà kíkan,eyín àwọn ọmọ sì kan.’

3. “Bí mo ti wà láàyè ni Olúwa Ọlọ́run wí, ẹ̀yin kó ni i pa òwe yìí mọ́ ni Ísírẹ́lì.

4. Nítorí pé èmi ló ní gbogbo ọkàn, ọkàn baba tèmi bẹ́ẹ̀ ni ọkàn ọmọ pàápá jẹ tèmi, ọkàn tó bá sẹ̀ ní yóò kú.

5. “Bí ọkùnrin Olódodo kan bá wà,tó ń ṣe ohun tó tọ́, tó sì yẹ

6. tí kò bá wọn jẹun lórí òkè gíga,tí kò gbójú rẹ̀ sókè sí àwọnòrìṣà ilẹ̀ Ísírẹ́lì, ti kò sì báobìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́ tàbí kí ósùn ti obìnrin ni àsìkò èérí rẹ̀.

7. Kò ní ẹnikẹ́ni lára,ó sì sanwó fún onígbésè rẹ̀ gẹ́gẹ́bó ṣe ṣe ìlérí fún un, kò fi ipájalè ṣùgbọ́n ó fún ẹni tí ebi ńpa ní oúnjẹ, tí ó sì fi ẹ̀wù wọàwọn tí ó wà ní ìhòòhò.

8. Kò yá ènìyàn ni owó ẹ̀dá tàbí kò gba èlétó pọ̀jù. Ó yọ ọwọ́ rẹ̀ kúrò nínúìwà ẹ̀ṣẹ̀, ó sì ń ṣe ìdájọ́ àìṣègbèláàrin ọkùnrin kan àti èkejì rẹ̀.

9. Tí ó ń tẹ̀lé àsẹ mi,tí ó sì ń pa òfin mi mọ́ lotítọ́ àti lódodo.Ó jẹ́ olódodo,yóò yè nítòótọ́,ní Olúwa Ọlọ́run wí.

10. “Bí ó bá bi ọmọkùnrin, oniwà ipá, tó ń jalè, tó tún ń pànìyàn tó sì ń ṣe gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí sí arákùnrin rẹ̀

11. (bó tilẹ̀ jẹ́ pé baba rẹ kò se irú rẹ̀):“Ó ń jẹun lojúbọ lórí òkè gíga,o ba ìyàwó aládùúgbò rẹ̀ jẹ́.

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 18