Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 16:36-42 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

36. Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run wí: Nítorí pé ìwọ tú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ jáde, ìwọ sì fi ìhòòhò rẹ hàn, nípa ṣíṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn olólùfẹ̀ẹ̀ rẹ, àti nítorí gbogbo ère tí o fi ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ rẹ ṣe ìrúbọ fún,

37. nítorí náà, Èmi yóò ṣa gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ jọ, pẹ̀lú gbogbo àwọn ti ẹ jọ ṣe fàájì, àwọn tí ìwọ fẹ́ àti àwọn tí ìwọ korìíra. Èmi yóò ṣa gbogbo wọn káàkiri, láti mú wọn lòdì sí ọ, èmi yóò sí aṣọ rẹ, níwájú wọn, wọn yóò sì rí ìhòòhò rẹ.

38. Èmi yóò dá ọ lẹ́jọ́, gẹ́gẹ́ bí a ti dá obìnrin tó ba ìgbeyàwó jẹ́, tí wọn sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀; Èmi yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ ìbínú àti owú mi wá sórí rẹ.

39. Nígbà náà ni èmi yóò fà ọ lé àwọn olólùfẹ́ rẹ lọ́wọ́, wọn yóò sì wó gbogbo òkìtì rẹ pẹ̀lú àwọn ojúbọ rẹ palẹ̀. Wọn yóò tú aṣọ kúrò lára rẹ̀, gbogbo ọ̀ṣọ́ rẹ ni wọn yóò gbà, wọn yóò sì fi ọ sílẹ̀ ní ìhòòhò àti ààbò.

40. Wọn yóò pe àjọ ènìyàn jọ lé ọ lórí, àwọn tí yóò sọ ọ́ ní òkúta, ti wọn yóò sì fi idà wọn gé ọ sí wẹ́wẹ́.

41. Wọn yóò jo gbogbo ilé rẹ palẹ̀ wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ́ ní ojú àwọn obìnrin. Èmi yóò fi òpin sí àgbèrè ṣíṣe rẹ. Ìwọ kò sì ní san owó fún àwọn olólùfẹ́ rẹ mọ́.

42. Nígbà náà ni ìbínú mi sí Ọ yóò rọ̀, owú ìbínú mi yóò sì kúrò lọ́dọ̀ rẹ; inú mi yóò rọ, èmi kò sì ní bínú mọ́.

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 16