Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Hósíà 8:2-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Ísírẹ́lì kígbe pè mí‘Áà! Ọlọ́run wa, àwa mọ̀ ọ́!’

3. Ṣùgbọ́n Ísírẹ́lì ti kọ ohun tí ó dára sílẹ̀ọ̀tá yóò sì máa lépa rẹ̀

4. Wọ́n fi àwọn ọba jẹ ṣùgbọ́n, kì í ṣe nípasẹ̀ miwọ́n yan ọmọ aládé láì si ìmọ̀ mi nibẹ̀.Wọ́n fi fàdákà àti wúràṣe ère fún ara wọn,kì a ba le ké wọn kúrò.

5. Ọmọ-mààlu rẹ ti ta ọ́ nù ìwọ Ṣamáríà! Ju ère tí o gbẹ́ nùÌbínú mi ń ru sí wọn:yóò ti pẹ́ tó kí wọ́n tó dé ipò àìmọ̀kan?

6. Ísírẹ́lì ni wọ́n ti wá!Ère yìí—agbẹ́gilére ló ṣe éÀní ère Samáríà, ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́.

7. “Wọ́n gbin afẹ́fẹ́wọ́n sì ká ìjìIgi ọkà kò lórí,kò sì ní mú oúnjẹ wá.Bí ó bá tilẹ̀ ní ọkààwọn àlejò ni yóò jẹ.

8. A ti gbé Ísírẹ́lì mì,Báyìí, ó sì ti wà láàrin àwọn orílẹ̀ èdèbí ohun èlò tí kò wúlò.

9. Nítorí pé wọ́n ti gòkè lọ sí Síríàgẹ́gẹ́ bí ẹhànnà kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tó ń rìn kiri.Éfúráímù ti ta ara rẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀.

10. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ti ta ara wọn sí àárin orílẹ̀ èdèÈmi ó ṣà wọ́n jọ nísinsìn yìíWọn ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣòfò dànùlọ́wọ́ ìnílára ọba alágbára.

11. “Nítorí Éfúráímù ti kọ́ pẹpẹ púpọ̀ fún ìrúbọ ẹ̀ṣẹ̀gbogbo rẹ̀ ti di pẹpẹ ìdẹ́ṣẹ̀ fún un

12. Mo kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun tí ó jẹ́ òfin mi fún wọn.Ṣùgbọ́n wọn kà á sí ohun àjèjì

Ka pipe ipin Hósíà 8