Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Hósíà 4:1-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọmọ Ísírẹ́lì,nítorí pé Olúwa fi ẹ̀sùnkan ẹ̀yin tí ń gbé ní ilẹ̀ náà.“Kò sí ìwà òtítọ́, kò sí ìfẹ́Kò sí ìmọ̀ Ọlọ́run ní ilẹ̀ náà

2. Afi èpè, irọ́ pípa àti ìpànìyànolè jíjà àti panṣágà.Wọ́n rú gbogbo òfin,ìtàjẹ̀sílẹ̀ sì ń gorí ìtàjẹ̀sílẹ̀.

3. “Nítorí èyí, ilẹ̀ náà ń ṣọ̀fọ̀, gbogboolùgbé ibẹ̀ sì ń ṣòfò dànù.Ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀runàti ẹja inú omi ló ń kú.

4. “Ṣùgbọ́n kí ẹnikẹ́ni má ṣe mú ẹ̀sùn wá,kí ẹnìkan má sì ṣe fi ẹ̀sùn kan ẹ̀nìkéjìnítorí àwọn ènìyàn rẹ̀ dàbíàwọn ti ń fi ẹ̀sùn kan àlùfáà

5. Ẹ ń ṣubú lọ́sàn-án àti lóruàwọn wòlíì yín sì ń ṣubú pẹ̀lúu yínÈmi ó pa ìyá rẹ run

6. Àwọn ènìyàn mi ń ṣègbé nítorí pé wọn kò ní ìmọ̀“Nítorí pé ẹ ti kọ ìmọ̀ sílẹ̀.Èmi náà kọ̀ yín ní àlùfáà mi;nítorí pé ẹ ti kọ òfìn Ọlọ́run yín sílẹ̀Èmi náà yóò gbàgbé àwọn ọmọ yín.

7. Bí àwọn àlùfáà ṣe ń pọ̀ sí ibẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń dẹ́ṣẹ̀ sí mi.Wọ́n yí ògo mi padà sí ohun ìtìjú

Ka pipe ipin Hósíà 4