Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Hósíà 2:16-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. “Yóò si ṣe ní ọjọ́ náàÌwọ yóò pè mí ní ‘Ọkọ mi’;Ìwọ kò sì ní pè mí ní ‘olúwa à mi mọ́,’ni Olúwa wí.

17. Èmi yóò mú orúkọ, àwọn òrìṣà Báálì kúrò lẹ́nu rẹ̀;ìwọ kò sì ní rí orúkọ òrìṣà Báálì pè mọ́

18. Ní ọjọ́ náà, èmi yóò ṣe májẹ̀múfún wọn àti àwọn ẹranko ìgbẹ́ àti ẹyẹ ojú ọ̀run àtiàwọn ẹ̀dá tí ń rìn lórí ilẹ̀.Kí wọn má bà á bẹ̀rù ara wọn mọ́Ọrun, idà àti ogun jíjà ni èmi ó parun ní ilẹ̀ náàkí gbogbo ènìyàn bá a lè wà ní àìléwu.

19. Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi títí láé.Èmi ó fẹ́ ọ ní ìwà òdodo àtiòtítọ́, ní ìfẹ́ àti àánú.

20. Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi ní ìsòtítọ́ìwọ yóò sì mọ Olúwa

21. “Èmi yóò sì dáhùn ní ọjọ́ náà”ni Olúwa wí.“Èmi yóò dá àwọn ọ̀run lóhùnàwọn ọ̀run yóò sì dá ilẹ̀ lóhùn;

22. Ilẹ̀ náà yóò sì dá ọkà,wáìnì tuntun àti òróró lóhùnGbogbo wọn ó sì dá Jésírẹ́lì lóhùn.

23. Èmi ó sì gbìn-ín fún ara mi lórí ilẹ̀ náàÈmi yóò ṣàánú fún ẹni tí kò tì í ri ‘àànú Gbà.’Èmi yóò sọ fún àwọn tí ‘Kì í ṣe ènìyàn mi pé,’‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi’; àwọn náà yóò sì wí pé, ‘Ìwọ ni Ọlọ́run mi.’ ”

Ka pipe ipin Hósíà 2