Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Hósíà 2:13-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Èmi yóò jẹ́ ẹ́ níyà fún gbogbo ọjọ́tó fi jo tùràrí sí Báálìtí ó fi òrùka àti ohun ọ̀ṣọ́ wọ ara rẹ̀ tán,tó sì tẹ̀lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ lọ.Ṣùgbọ́n ó gbàgbé èmi,”ni Olúwa wí.

14. “Nítorí náà, èmi yóò tàn ánÈmi ó sì mú u lọ sí ilẹ̀ aṣálẹ̀Èmi ó fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ bá a sọ̀rọ̀

15. Níbẹ̀ ni èmi yóò ti dá ọgbà àjàrà rẹ̀ padà fún un,Èmi yóò fi àfonífojì Ákórì ṣe ilẹ̀kùn ìrètí fún un.Yóò sì kọrin níbẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà èwe rẹ̀gẹ́gẹ́ bí ìgbà tó kúrò ní Éjíbítì

Ka pipe ipin Hósíà 2