Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Hósíà 11:5-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. “Ṣé wọn ò wá ní padà sí Éjíbítì bíṢé Ásíríà kò sì ní jẹ ọba lé wọn lórí bínítorí pé wọ́n kọ̀ jálẹ̀ láti ronú pìwàdà?

6. Idà yóò kọ mọ̀nà ní gbogbo ìlú wọnyóò si bá gbogbo irin ẹnú odi ìlú wọn jẹ́yóò sì fòpin sí gbogbo èrò wọn.

7. Àwọn ènìyàn mi ti pinnu láti pẹ̀yìndà kúrò lọ́dọ̀ miBí wọ́n tilẹ̀ pè wọ́n sọ́dọ̀ ọ̀gá-ògo júlọ,kò ní gbé wọn ga rárá.

8. “Báwo ni èmi ó ṣe fi ọ́ sílẹ̀, Éfúráímù?Báwo ni èmi ó ṣe yọ̀ǹda rẹ̀, Ísírẹ́lìBáwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Ádímà?Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Ṣébóímù?Ọkàn mi yípadà nínú miÀánú mi sì ru sókè

9. Èmi kò ni i mú ìbínú gbígbóná mi ṣẹtàbí kí èmi wá sọ Éfúráímù di ahoroNítorí pé Ọlọ́run ni àni, èmi kì í ṣe ènìyànẸni mímọ́ láàrin yín,Èmi kò ni i wa nínú ìbínú

10. Wọn yóò máa tẹ̀lé Olúwa;òun yóò bú ramúramù bí i kìnnìúnNígbà tó bá búàwọn ọmọ yóò wá ní ìwárìrì láti ìwọ̀ oòrùn.

11. Wọn ó wá pẹ̀lú ẹ̀rùbi i ẹyẹ láti Éjíbítìbi i àdàbà láti ÁsíríàÈmi ó mú wọn padà sí ilé wọn,”ni Olúwa wí.

12. Éfúráímù tí fi irọ́ yí mi káilé Ísírẹ́lì pẹ̀lú ẹ̀tàn.Ṣùgbọ́n Júdà sì dúró ṣinṣin pẹ̀lú Ọlọ́runÓ sì ṣe olóòótọ́ sí Ẹni mímọ́ Ísírẹ́lì.

Ka pipe ipin Hósíà 11