Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Hágáì 2:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní ọjọ́ kọkànlélógún oṣù keje, ni ọ̀rọ̀ Olúwa wá nípaṣẹ̀ wòlíì Hágáì wí pé:

2. “Sọ fún Sérúbábélì ọmọ Séítélì, olórí Júdà, àti Jóṣúà ọmọ Jósédékì, olórí àlùfáà àti àwọn ènìyàn yòókù. Béèrè lọ́wọ́ wọn pé,

3. ‘Ta ni nínú yín tí ó kù tí ó sì ti rí ilé yìí ní ògo rẹ̀ àkọ́kọ́? Báwo ni ó ṣe ri sí yín nísinsin yìí? Ǹjẹ́ kò dàbí asán lójú yín?

4. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, múra gírí, ìwọ Sérúbábélì,’ ni Olúwa wí. ‘Múra gírí, ìwọ Jóṣúà ọmọ Jósédékì, olórí àlùfáà. Ẹ sì múra gírí gbogbo ẹ̀yin ènìyàn ilẹ̀ náà;’ ni Olúwa wí, ‘kí ẹ sì ṣiṣẹ́. Nítorí èmi wà pẹ̀lú yín;’ ni Olúwa àwọn ọmọ ogun wí.

5. ‘Èyí ni ohun tí Èmi fi bá a yín dá májẹ̀mú nígbà tí ẹ jáde kúrò ní Éjíbítì, bẹ́ẹ̀ ni Ẹ̀mí ì mi sì wà pẹ̀lú yín. Ẹ má ṣe bẹ̀rù.’

6. “Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Láìpẹ́ jọjọ, Èmi yóò mi àwọn ọrun àti ayé, òkun àti ìyàngbẹ ilẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i.

7. Èmi yóò mi gbogbo orílẹ̀ èdè, ìfẹ́ gbogbo orílẹ̀ èdè yóò fà sí Tẹ́ḿpìlì yìí, Èmi yóò sì kùn ilé yìí pẹ̀lu ògo;’ ni Olúwa àwọn ọmọ ogun wí.

8. ‘Tèmi ni fàdákà àti wúrà,’ ni Olúwa àwọn ọmọ ogun wí.

Ka pipe ipin Hágáì 2