Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Hábákúkù 3:3-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Ọlọ́run yóò wa láti Témánì,Ibi mímọ́ jùlọ láti Òkè Páránìògo rẹ̀ sí bo àwọn ọ̀run,Ilé ayé sì kún fún ìyìn rẹ

4. Dídán rẹ ṣí dàbí ìmọ́lẹ̀;Ìmọ́lẹ̀ kọ-ṣàn-án láti ọwọ́ rẹ wá,níbi tí wọn fi agbára rẹ̀ pamọ́ sí.

5. Àjàkálẹ̀ àrùn ń lọ ni iwájú rẹ;ìyọnu ṣí ń tọ ẹsẹ̀ rẹ lọ.

6. Ó dúró, ó sì mi ayé;ó wò, ó sì mú àwọn orílẹ̀-èdè wárìrìa sì tú àwọn òkè-ńlá ayérayé ká,àwọn òkè kéékèèkéé ayérayé sì tẹríba:ọ̀nà rẹ ayérayé ni.

7. Mo rí àgọ́ Kúṣánì nínú ìpọ́njúàti àwọn ibùgbé Mídíanì nínú ìrora.

8. Ǹjẹ́ ìwọ ha ń bínú sí àwọn Odò nì, Olúwa?Ǹjẹ́ ìbínú rẹ wa lórí àwọn odò síṣàn bí?Ìbínú rẹ ha wá sórí òkuntí ìwọ fi ń gún ẹṣin,àti kẹ̀kẹ́ ìgbàlá rẹ?

9. Ìwọ kò bo ọrun rẹ,o sì pè fún ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ ọfàìwọ sì pín ayé níyà pẹ̀lú odò.

10. Àwọn òkè-ńlá ri ọ wọn ṣì wárìrìàgbàrá òjò ń ṣàn án kọjá lọ;ibú ń ké ramúramùó sì gbé irú omi sókè.

11. Òòrùn àti Òṣùpá dúró jẹ́ẹ́jẹ́ẹ́ ni ibùgbé wọn,pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ ọfà rẹ ni wọn yára lọ,àti ni dídán ọ̀kọ̀ rẹ ti ń kọ mànà.

12. Ní ìrúnú ni ìwọ rin ilẹ̀ náà já,ní ìbínú ni ìwọ tí tẹ́ àwọn orílẹ̀-èdè rẹ.

13. Ìwọ jáde lọ láti tú àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀,àti láti gba ẹni àmì òróró rẹ là;Ìwọ ti run àwọn olórí kúrò nínú ilẹ̀ àwọn ènìyàn búburú,fifi ìpìlẹ̀ hàn títí dé ọrùn

Ka pipe ipin Hábákúkù 3