Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ẹkún Jeremáyà 4:19-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Àwọn tí ń lé wa yáraju idì ojú ọ̀run lọ;wọ́n lé wa ní gbogbo orí òkèwọ́n sì gẹ̀gùn dè wá ní ihà.

20. Ẹni àmì òróró Olúwa, èémí ìyè wa,ni wọ́n fi tàkúté wọn mú.Àwa rò pé lábẹ́ òjìji rẹ̀ni àwa yóò máa gbé láàrin orílẹ̀-èdè gbogbo.

21. Ẹ yọ̀ kí inú yín sì dùn, ẹ̀yin ọmọbìnrin Édómù,ẹ̀yin tó ń gbé ní ilẹ̀ Húsì.Ṣùgbọ́n, a ó gbé aago náà kọjá sọ́dọ̀ rẹ pẹ̀lú;ìwọ yóò yó bí ọ̀mùtí, ìwọ yóò sì rìn ní ìhòòhò.

22. Ìwọ ọmọbìnrin Síónì, ìjìyà rẹ yóò dópin;kò ní mú ìgbékùn rẹ pẹ́ mọ́.Ṣùgbọ́n, ìwọ ọmọbìnrin Édómù, yóò jẹ ẹ̀sẹ̀ rẹ níyàyóò sì fi àìṣedédé rẹ hàn kedere.

Ka pipe ipin Ẹkún Jeremáyà 4