Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 4:26-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

26. Nítorí náà Olúwa yọ̀ǹda rẹ láti ìgbà tí ó ti wí pé, “Ẹlẹ́jẹ̀ ni ìwọ í ṣe.” Èyí tó túmọ̀ sí àkọlà abẹ́.

27. Olúwa sì sọ fún Árónì pé, “Lọ sínú ihà láti lọ pàdé Mósè.” Ní ìgbà náà ni ó lọ pàdé Mósè ní orí òkè Ọlọ́run, ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.

28. Ní ìgbà náà ni Mósè sì sọ ohun gbogbo tí Ọlọ́run ti sọ fún un àti nípa gbogbo iṣẹ́ ìyanu tí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún un láti ṣe ní iwájú Fáráò.

29. Mósè àti Árónì pe gbogbo àwọn àgbààgbà Ísírẹ́lì jọ.

30. Árónì sọ ohun gbogbo tí Olúwa sọ fún Mósè fún wọn

31. Wọ́n sì gbàgbọ́. Nígbà tí wọ́n gbọ́ pé Olúwa ti bẹ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì wò àti pé Olúwa ti gbọ́ nípa ìpọ́njú wọn, wọ́n tẹríba, wọ́n sì sìn ín. Ó sì ṣe àwọn iṣẹ́ amì náà níwájú àwọn ènìyàn náà.

Ka pipe ipin Ékísódù 4