Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 4:23-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

23. mo sọ fún ọ, “Jẹ́ kí ọmọ mi lọ, ki òun kí ó lè máa sìn mí.” Ṣùgbọ́n ìwọ kọ̀ láti jẹ́ kí ó lọ; nítorí náà, èmi yóò pa àkọ́bí ọmọ rẹ ọkùnrin.’ ”

24. Ní ọ̀nà ìrìnàjò rẹ, ni ibi tí wọ́n gbé sùn ní ilé-èrò ní alẹ́, Olúwa pàdé Mósè, ó sì fẹ́ láti pa á.

25. Ṣùgbọ́n Ṣípórà mú ọ̀bẹ òkúta mímú, ó sì kọ ọmọ rẹ̀ ní ilà abẹ́, ó si fi awọ rẹ̀ kan ẹṣẹ̀ Mósè. Ṣípórà sì wí pé, “Ọkọ ẹlẹ́jẹ̀ ni ìwọ jẹ́ sí mi.”

26. Nítorí náà Olúwa yọ̀ǹda rẹ láti ìgbà tí ó ti wí pé, “Ẹlẹ́jẹ̀ ni ìwọ í ṣe.” Èyí tó túmọ̀ sí àkọlà abẹ́.

27. Olúwa sì sọ fún Árónì pé, “Lọ sínú ihà láti lọ pàdé Mósè.” Ní ìgbà náà ni ó lọ pàdé Mósè ní orí òkè Ọlọ́run, ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.

28. Ní ìgbà náà ni Mósè sì sọ ohun gbogbo tí Ọlọ́run ti sọ fún un àti nípa gbogbo iṣẹ́ ìyanu tí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún un láti ṣe ní iwájú Fáráò.

29. Mósè àti Árónì pe gbogbo àwọn àgbààgbà Ísírẹ́lì jọ.

Ka pipe ipin Ékísódù 4