Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 36:25-38 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

25. Fún ìhà kejì, ìhà àríwá Àgọ́ náà, wọ́n ṣe ogún pákó

26. ogójì (40) fàdákà ihò ìtẹ̀bọ̀ méjì ní ìṣàlẹ̀ pákó kọ̀ọ̀kan.

27. Wọ́n ṣe pákó mẹ́fà sì ìkángun, ní ìkangun ìhà ìwọ̀ oòrùn Àgọ́ náà,

28. pákó méjì ni wọ́n ṣe sí igun Àgọ́ náà ní ìkangun.

29. Ní igun méjèèjì yìí, pákó méjì ni ó wà níbẹ láti ìdí dé orí rẹ̀ wọ́n sì kó wọ́n sí òrùka kan; méjèèjì rí bákan náà.

30. Wọ́n jẹ́ pákó mẹ́jọ àti fàdákà mẹ́rìn-lélógún ìhò ìtẹ̀bọ̀, méjì wà ní ìṣàlẹ̀ kọ̀ọ̀kan.

31. Wọ́n sì tún ṣe ọ̀pá igi kaṣíà: márùn ún fún pakó ní ìhà kọ̀ọ̀kan Àgọ́ náà,

32. márùn-ún fún àwọn tí ó wà ní ìhà kejì, márùn-ún fún pákó tí ó wà ní ìhà ìwọ̀ oòrùn ní ìkangun Àgọ́ náà.

33. Wọ́n sì ṣe ọ̀pá àárin tí yóò fi jáde láti ìkangun dé ìkangun ní àárin àwọn pákó náà.

34. Wọ́n bo àwọn pákó pẹ̀lú wúrà, wọ́n sì ṣe àwọn òrùkà wúrà láti gbá ọ̀pá náà mú. Wọ́n sì tún bo ọ̀pá náà pẹ̀lú wúrà.

35. Wọ́n ṣe aṣọ títa ti aṣọ aláró, ti elésèé àlùkò, ti òdòdó àti ti ọ̀gbọ̀ olókùn dáradára, wọ́n ṣe kérúbù si pẹ̀lú ọgbọ́n oníṣẹ́ ọnà.

36. Wọ́n sì ṣe òpó igi kasíá mẹ́rin fún-un wọ́n sì bò wọ́n pẹ̀lú wúrà. Wọ́n sì ṣe àwọn ìkọ́ wúrà fún wọn, wọ́n sì gba ihò ìtẹ̀bọ̀ fàdákà mẹ́rin wọn.

37. Fún ẹnu ọ̀nà Àgọ́ náà wọ́n ṣe aṣọ títa ti aṣọ aláró, ti elésèé àlùkù, ti òdòdò àti ti ọ̀gbọ̀ olókùn dáradára iṣẹ́ abẹ́rẹ́;

38. wọ́n sì ṣe òpó márùn-ún pẹ̀lú ìkọ́ wọn. Wọ́n bo orí àwọn òpó náà àti ìgbànú wọn pẹ̀lú wúrà, wọn sì ṣe ihò ìtẹ̀bọ̀ márùn-ún wọn ní idẹ.

Ka pipe ipin Ékísódù 36