Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 36:1-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Bésálélì, Óhólíábù àti olúkúlùkù ọlọ́gbọ́n ẹni tí Olúwa tí fún ní ọgbọ́n àti agbára láti mọ bí a ti í ṣe gbogbo iṣẹ́ ibi mímọ́ ni kí wọn ṣe iṣẹ́ náà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ.”

2. Mósè sì pe Bésálélì àti Óhóábù àti gbogbo ọlọ́gbọ́n ènìyàn ẹni tí Olúwa ti fún ni agbára àti gbogbo ẹni tí ó fẹ́ láti wá sé iṣẹ́ náà.

3. Wọ́n gba gbogbo ọrẹ tí àwọn ọmọ Isirẹli ti mú wá lọ́wọ́ Mósè fún kíkọ́ ibi mímọ́ náà. Àwọn ènìyàn sì ń mú ọrẹ àtinúwá wá ní àràárọ̀.

4. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo àwọn ọlọ́gbọ́n oníṣẹ́ ọnà tí wọn ń ṣe gbogbo iṣẹ́ ibi mímọ́ náà fi iṣẹ́ wọn sílẹ̀.

5. Mósè sì wí pé, “Àwọn ènìyàn mú púpọ̀ wá fún síṣe iṣẹ́ náà ju bi Olúwa ti pa á láṣẹ láti ṣe lọ.”

6. Mósè sì pàṣẹ, wọ́n sì rán iṣẹ́ yìí sí gbogbo ibùdó: “Kí ọkùnrin tàbí obìnrin má ṣe ṣe ohun kankan bí ọrẹ fún ibi mímọ́ náà mọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni a dá àwọn ènìyàn lẹ́kun láti mú un wá sí i,

7. nítorí ohun tí wọ́n ti ni ti ju ohun tí wọn fẹ́ fi ṣe gbogbo iṣẹ́ náà lọ.

8. Gbogbo àwọn ọlọ́gbọ́n ọkùnrin láàrin àwọn òṣìṣẹ́ ni wọ́n ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú aṣọ títa mẹ́wàá ti ọ̀gbọ̀ olókùn dáradára, tí aṣọ aláró, ti elésèé àlukò àti ti òdòdó, pẹ̀lú àwọn kérúbù ṣe iṣẹ́ sí wọn nípa ọgbọ́n iṣẹ́ ọnà.

9. Gbogbo aṣọ títa náà jẹ́ ìwọ̀n kan ìgbọ̀nwọ́ méjìdínlọ́gbọ̀n (28) ní gíga àti ìgbọ̀nwọ́ mẹ́rin ní fífẹ̀.

10. Wọ́n sì pa aṣọ títa márùn-ún pọ̀ mọ̀ ara wọn, wọ́n sì tún ṣe bẹ́ẹ̀ sì márùn-ún tó kù.

11. Wọ́n sì pa ajábó aṣọ aláró ní etí aṣọ títa kan láti ìsẹ́tí rẹ̀ dé ibi òpin, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ní o ṣe sí ìhà etí ikangun aṣọ títa kejì ní ibi òpin èkejì.

12. Àádọ́ta (50) ajábó ní ó pa lára aṣọ títa kan, àti àádọ́ta ajábó ni ó sì lò pa ní etí aṣọ títa tí ó wà ní ọ̀kánkán ara wọn.

13. Wọ́n sì ṣe àádọ́ta ìkọ́ wúrà, ó sì lò wọ́n láti fi kọ́ méjì aṣọ títa papọ̀ bẹ́ẹ̀ Àgọ́ náà sì di ọ̀kan.

14. Wọ́n ṣe aṣọ títa ti irun ewúrẹ́ fún Àgọ́ náà lórí Àgọ́ náà mọ́kànlá ni gbogbo rẹ̀ papọ̀.

Ka pipe ipin Ékísódù 36