Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 3:9-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Ǹjẹ́ nísinsìnyìí, wò ó, igbe àwọn ará Ísírẹ́lì ti dé ọ̀dọ̀ mi, Èmi sì ti rí bí àwọn ará Éjíbítì ti se ń gbà ń jẹ wọ́n ní ìyà.

10. Ǹjẹ́ nísinsínyìí, lọ, Èmi yóò rán ọ sí Fáráò láti kó àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì jáde kúrò ní ilẹ̀ Éjíbítì.”

11. Ṣùgbọ́n Mósè wí fún Ọlọ́run pé, “Ta ni èmi, tí èmi yóò tọ Fáráò lọ, ti èmi yóò sì kó àwọn ará Ísírẹ́lì jáde kúrò ni ilẹ̀ Éjíbítì?”

12. Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Mósè pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ̀. Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún ọ, tí yóò fihàn pé Èmi ni ó rán ọ lọ; Nígbà tí ìwọ bá kó àwọn ènìyàn náà jáde kúrò ní ilẹ̀ Éjíbítì, ẹ̀yin yóò sin Ọlọ́run ni orí òkè yìí.”

13. Mósè sì wí fún Ọlọ́run pé, “Bí mo bá tọ̀ àwọn ará Ísírẹ́lì lọ ti mo sì sọ fún wọn pé, ‘Ọlọ́run àwọn baba yín ni ó rán mi sí i yín,’ tí wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ mi pé, ‘Kí ni orúkọ rẹ̀?’ Kí ni èmi yóò sọ fún wọn ní ìgbà náà?”

Ka pipe ipin Ékísódù 3