Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 22:22-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

22. “Má ṣe yan opó tàbí ọmọ òrukàn jẹ.

23. Bí ìwọ bá se bẹ́ẹ̀, bí wọn bá ké pè mi. Èmi yóò sì gbọ́ ohùn igbe wọn.

24. Ìbínú mi yóò ru sókè. Èmi yóò sì fi idà pa ọ. Ìyàwó rẹ yóò di opó, àwọn ọmọ rẹ yóò sì di aláìní baba.

25. “Bí ìwọ bá yá ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn mi tí ìyà ń jẹ láàrin yín lówó, má ṣe dàbí ayánilówó, kí o má sì gba èlé.

26. Bí ìwọ bá gba aṣọ aládùúgbò rẹ ni ẹ̀jẹ́, ìwọ gbọdọ̀ fún un padà kí òòrùn tó ó wọ̀,

27. Nítorí aṣọ yìí nìkan ní ó ní ti ó lè fi bo àṣírí ara. Kí ni ohun mìíràn ti yóò fi sùn? Nígbà ti ó bá gbé ohun rẹ̀ sókè sími, èmi yóò gbọ́ nítorí aláàánú ni èmi.

28. “Ìwọ kò gbọdọ̀ sọ̀rọ̀ òdì sí Ọlọ́run tàbí sẹ́ èpè lé orí ìjòyé àwọn ènìyàn rẹ.

29. “Ìwọ kò gbọdọ̀ lọ́ra láti mú ọrẹ wá fún mi láti inú ire oko rẹ àti láti inú wáìnì rẹ.“Àkọ́bí ọmọ rẹ ọkùnrin ni ìwọ yóò fi fún mi.

30. Ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ pẹ̀lú agbo màlúù rẹ àti agbo àgùntàn rẹ. Jẹ́ kí wọn wà lọ́dọ̀ ìyá wọn fún ọjọ́ méje, kí ìwọ kí ó sì fi wọ́n fún mi ní ọjọ kẹjọ.

31. “Ẹ̀yin yóò jẹ́ ènìyàn mímọ́ mi. Nítorí náà má ṣe jẹ ẹran ti ẹranko búburú fàya: ẹ fi fún ajá jẹ.

Ka pipe ipin Ékísódù 22