Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 21:12-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. “Ẹnikẹ́ni tí ó bá lu arákùnrin rẹ̀ pa, pípa ni a ó pa á.

13. Ṣùgbọ́n bí kò bá mọ̀ ọ́n mọ̀ pa á, tí ó bá jẹ́ (àmúwá) ìfẹ́ Ọlọ́run ni, òun yóò lọ sí ibi tí èmi yóò yàn fún un.

14. Ṣùgbọ́n tí ó bá arákùnrin rẹ̀, tí ó sì fi ẹ̀tàn pa á. Ẹ mú un kúrò ní iwájú pẹpẹ mi kí ẹ sì pa á.

15. “Ẹnikẹ́ni tí ó bá pa baba tàbí ìyá rẹ̀, pípa ni a ó pa á.

16. “Ẹnikẹ́ni ti ó bá ji ènìyàn gbé, tí ó sì tà á tàbí tí ó fi ì pamọ́, pípa ni a ó pa á.

17. “Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣépè fún baba tàbí ìyá rẹ̀, pípa ni a ó pa á.

18. “Bí àwọn ọkùnrin méjì bá ń jà, ti ọ̀kan sọ òkúta tàbí fi ẹ̀ṣẹ́ lu ẹnìkejì rẹ̀, tí ó sì pa á lára, ti irú ìpalára bẹ́ẹ̀ mu kí ó wà lórí ìdùbúlẹ̀ àìsàn,

19. Ẹni tó lu ẹnìkejì rẹ̀ kò ní ní ẹ̀bi, níwọ̀n ìgbà ti ẹni tí a lù bá ti lè dìde, tí ó sì lé è fi ọ̀pá ìtilẹ̀ ní ọwọ rẹ̀ rìn káàkiri. Ẹni náà ni láti san owo ti ó fi tọ́jú ara rẹ̀ padà fún un, lẹ́yìn ìgbà tí ara rẹ̀ bá ti yá tan pátápátá.

20. “Bí ọkùnrin kan bá fi ọ̀pá lu ẹrúkùnrin tàbí ẹrubìnrin rẹ̀, ti ẹrú náà sì kú lójú ẹṣẹ̀, a ó fi ìyà jẹẹ́.

21. Ṣùgbọ́n a kò ní fi ìyà jẹ̀ ẹ́, ti ẹrú náà bá yè, tí ó dìde lẹ́yìn ọjọ́ kan tàbí méjì, nítorí ẹrú náà jẹ́ dúkìá rẹ̀.

22. “Bí àwọn ènìyàn ti ń jà bá pa aboyún lára, tí aboyún náà bá bimọ láìpé ọjọ́, ṣùgbọ́n ti kò sí aburú mìíràn mọ́ lẹ́yìn rẹ̀, ẹni ti ó fa ìpalára yìí yóò san iyekíye ti ọkọ aboyún náà bá béèrè fún, bí ilé ẹjọ́ bá se gbà láàyè gẹ́gẹ́ bí owó ìtanràn.

Ka pipe ipin Ékísódù 21