Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 14:18-30 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Àwọn ará Éjíbítì yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa nígbà ti èmi bá gba ògo fún ara mi lórí Fáráò: lórí kẹ̀kẹ́-ogun rẹ̀ àti lórí àwọn ẹlẹ́sin rẹ̀.”

19. Nígbà náà ni ańgẹ́lì Ọlọ́run tó ti ń ṣááju ogun Ísírẹ́lì lọ, padà o sì rìn ni ẹ̀yìn wọn; Òpó ìkùùkuu tí ń rìn ni iwájú wọn sì padà sí í rìn ni ẹ̀yìn wọn.

20. Ó sì wà láàrin àwọn ọmọ ogun Éjíbítì àti Ísírẹ́lì. Ìkùùkuu sì su òkùnkùn sí àwọn ará Éjíbítì ni òru náà. Ṣùgbọ́n ó tan ìmọ́lẹ̀ sí àwọn Ísírẹ́lì ni òru náà; Ọ̀kan kò sì súnmọ́ èkejì ni gbogbo òru náà.

21. Nígbà náà ni Mósè na ọwọ́ rẹ̀ sí orí òkun, ni gbogbo òru náà ni Olúwa fi lé òkun sẹ́yìn pẹ̀lú ìjì líle láti ìlà-oòrùn wá, ó sì sọ ọ́ di ìyàngbẹ ilẹ̀. Omi òkun sì pínyà,

22. àwọn ọmọ Ísírẹ́lì si la ìyàngbẹ ilẹ̀ kọjá nínú òkun pẹ̀lú ògiri omi ní ọ̀tún àti òsì.

23. Àwọn ará Éjíbítì sì ń lépa wọn, gbogbo ẹsin Fáráò, kẹ́kẹ́-ogun àti àwọn ẹlẹ́sin rẹ̀ wọ́ tọ̀ wọ́n lọ sínú òkun.

24. Ní ìsọ́ òwúrọ̀ (láàárin ago mẹ́ta sí mẹ́ta òwúrọ̀) Olúwa bojúwo ogun àwọn ará Éjíbítì láàrin òpó iná àti ìkùùkuu, ó sì kó ìpayà bá àwọn ọmọ ogun Éjíbítì.

25. Ó sì yọ àgbá ẹsẹ̀ kẹ̀kẹ́ ogun wọn kí ó bá à le ṣòro fún wọn láti fi kẹ̀kẹ́-ogun náà rìn. Àwọn ará Éjíbítì wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sá àṣálà kúrò ní iwájú àwọn ará Ísírẹ́lì nítorí Olúwa ń bá wa jà nítorí wọn.”.

26. Olúwa sì wí fún Mósè pé, “Na ọwọ́ rẹ sí orí òkun kí omi òkun lè ya padà sórí àwọn ará Éjíbítì, kẹ̀kẹ́ ogun wọn àti sórí ẹlẹ́sin wọn.”

27. Mósè sì na ọwọ́ rẹ̀ sí orí òkun, òkun sì padà bọ́ sí ipò rẹ̀ nígbà ti ìlẹ̀ mọ́. Àwọn ará Éjíbítì ń sá fún omi òkun, Olúwa sì gbá wọn sínú òkun.

28. Omi òkun sì ya padà, ó sì bo kẹ̀kẹ́-ogun àti àwọn ẹlẹ́sin: àní, gbogbo ọmọ ogun Fáráò ti wọn wọ inú òkun tọ̀ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì lọ kò sí ọ̀kan nínú wọn ti o yè.

29. Ṣùgbọ́n àwọn ará Ísírẹ́lì la òkun kọjá lórí ìyàngbẹ ilẹ̀ pẹ̀lú ògiri omi ni ọ̀tún àti òsì wọn.

30. Ni ọjọ́ yìí ni Olúwa gba Ísírẹ́lì là kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Éjíbítì; Ísírẹ́lì sì rí òkú àwọn ará Éjíbítì ni etí òkun.

Ka pipe ipin Ékísódù 14