Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Deutarónómì 5:1-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Mósè sì pe gbogbo Ísírẹ́lì jọ, ó sì wí pé: Gbọ́ ìwọ Ísírẹ́lì, gbọ́ ìlànà àti òfin tí mo mú wá sí etíìgbọ ọ yín lónìí. Ẹ kọ wọ́n, kí ẹ sì ri dájú pé ẹ̀ ń ṣe wọ́n.

2. Olúwa Ọlọ́run wa bá wa dá májẹ̀mú ní Hórébù.

3. Kì í ṣe àwọn baba wa ni Olúwa bá dá májẹ̀mú yìí bí kò ṣe àwa, àní pẹ̀lú gbogbo àwa tí a wà láàyè níbí lónìí.

4. Olúwa bá a yín sọ̀rọ̀ lójúkojú láàrin iná lórí òkè.

5. (Ní ìgbà yìí, mo wà láàrin ẹ̀yin pẹ̀lú Ọlọ́run láti sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run fún un yín torí pé ẹ̀rù Ọlọ́run ń bà yín, ẹ kò sì lè kọjá lọ sórí òkè) Ó sì wí pé:

6. “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú un yín jáde láti Íjíbitì láti oko ẹrú wá.

7. “Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ ní Ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú ù mi.

Ka pipe ipin Deutarónómì 5