Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Deutarónómì 32:2-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Jẹ́kí ẹ̀kọ́ ọ̀ mi máa rọ̀ bí òjò,kí awọn ọ̀rọ̀ mi máa ṣọ̀kalẹ̀ bí ìrì,bí òjò winiwini sára ewéko túntún,bí ọ̀wàrà òjò sára ohun ọ̀gbìn.

3. Èmi yóò kókìkí orúkọ Olúwa,Áà, ẹ yìn títóbi Ọlọ́run wa!

4. Òun ni àpáta, iṣẹ́ ẹ rẹ̀ jẹ́ pípé,gbogbo ọ̀nà an rẹ̀ jẹ́ òdodo.Ọlọ́run olótìítọ́ tí kò ṣe àsìṣe kan,Ó dúró ṣinṣin, òdodo àti òtítọ́ ni òun.

5. Wọ́n ti ṣe iṣẹ́ ìbàjẹ́ sọ́dọ̀ ọ rẹ̀;fún ìtìjú u wọn, wọn kì í ṣe ọmọ rẹ̀ mọ́,ṣùgbọ́n ìran tí ó yí sí apákan tí ó sì doríkodò.

6. Ṣé báyìí ni ẹ̀yin yóò ṣe san an fún Olúwa,Áà ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìgbọ́n ènìyàn?Ǹjẹ́ òun kọ́ ni baba yín, Ẹlẹ́dàá yín,tí ó dá a yín tí ó sì mọ yín?

7. Rántí ìgbà láéláé;wádìí àwọn ìran tí ó ti kọjá.Béèrè lọ́wọ́ baba à rẹ yóò sì sọ fún ọ,àwọn àgbà rẹ, wọn yóò sì ṣàlàyé fún ọ.

8. Nígbà tí atóbijù fi ogún àwọn orílẹ̀ èdè fún wọn,nígbà tí ó pín onírúurú ènìyàn,ó sì gbé ààlà kalẹ̀ fún àwọn ènìyàngẹ́gẹ́ bí iye ọmọkùnrin Ísírẹ́lì.

9. Nítorí ìpín Olúwa ni àwọn ènìyàn an rẹ̀,Jákọ́bù ni ìpín ìní i rẹ̀.

10. Ní ihà ni ó ti rí i,ní ihà níbi tí ẹranko kò sí.Ó yíká, ó sì tọ́jú u rẹ̀,ó pa á mọ́ bí ẹyin ojú u rẹ̀.

11. Bí idì ti íru ìtẹ́ rẹ̀ ti ó sì ńrábàbà sórí ọmọ rẹ̀,tí ó na ìyẹ́ apá rẹ̀ láti gbé wọn ki ó sìgbé wọn sórí ìyẹ́ apá rẹ̀.

12. Olúwa samọ̀nà;kò sì sí ọlọ́run àjèjì pẹ̀lú rẹ̀.

13. Ó mú gun ibi gíga ayéó sì fi èṣo oko bọ́ ọ.Ó sì jẹ́ kí ó mú oyin láti inú àpáta wá,àti òróró láti inú akọ òkúta wá,

14. Pẹ̀lú u wàràǹkàsì àti wàrà àgùntànàti ti àgbò ẹranàti pẹ̀lú ọ̀rá ọ̀dọ́ àgùntàn àti ewúrẹ́,pẹ̀lú àgbò irú u ti Báṣánìtí ó sì mu ẹ̀jẹ̀ èṣo-àjàrà, àní àti wáìnì.

15. Jéṣúrúnì sanra tán ó sì tàpá;ìwọ ṣanra tán, ìwọ ki tan, ọ̀rá sì bò ọ́ tán.O kọ Ọlọ́run tí ó dá ọo sì kọ àpáta ìgbàlà rẹ.

16. Wọ́n sì fi jowú pẹ̀lú ọlọ́run àjèjì i wọnwọ́n sì mú un bínú pẹ̀lú àwọn òrìṣà a wọn.

17. Wọ́n rúbọ sí iwin búburú, tí kì í ṣe Ọlọ́run,ọlọ́run tí wọn kò mọ̀ rí,ọlọ́run tí ó sẹ̀sẹ̀ farahàn láìpẹ́,ọlọ́run tí àwọn baba yín kò bẹ̀rù.

Ka pipe ipin Deutarónómì 32