Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Dáníẹ́lì 10:18-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Ẹ̀wẹ̀, ẹnìkan tí ó rí bí ènìyàn fi ọwọ́ kàn mí, ó sì fún mi ní agbára.

19. Ó sì wí pé, “Má se bẹ̀rù, ìwọ ọkùnrin tí a yàn fẹ́ gidigidi.” Bí ó ti sọ̀rọ̀ fún mi, ara à mí sì le, mo sọ pé, “Má a wí Olúwa mi, níwọ̀n ìgbà tí o ti fún mi ní agbára.”

20. Nígbà náà, ni ó wí pé, “Sé o mọ ìdí tí mo fi tọ̀ ọ́ wá? Láìpẹ́ èmi yóò yípadà lọ bá àwọn ọmọ aládé Páṣíà jà, nígbà tí mo bá lọ àwọn ọmọ aládé Gíríkì yóò wá;

21. ṣùgbọ́n ní àkọ́kọ́, èmi yóò sọ ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé òtítọ́ fún ọ. (Kò sí ẹni tí ó kún mi lọ́wọ́ fún nǹkan wọ̀nyí bí kò ṣe Máíkẹ́lì, ọmọ aládé e yín.

Ka pipe ipin Dáníẹ́lì 10