Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ámósì 7:1-3 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run fi hàn mí: Ó pèsè ọwọ́ esú lẹ́yìn ìgbà tí a kórè ìpín ọba, ní ìgbà ti èso ẹ̀ẹ̀kejì ń jáde bọ̀.

2. Nígbà tí wọ́n jẹ koríko ilẹ̀ náà mọ́ féfé nígbà náà ni mo gbé ohùn mi sókè pé, “Olúwa Ọlọ́run, mo bẹ̀ ọ́, dáríjìn! Báwo ni Jákọ́bù yóò ha ṣe lè dìde? Òun kéré jọjọ!”

3. Olúwa ronúpìwàdà nípa èyí;“Èyí kò ni sẹlẹ̀,” ni Olúwa wí.

Ka pipe ipin Ámósì 7