Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ámósì 5:20-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. Ǹjẹ́ ọjọ́ Olúwa kò ha ní ṣókùnkùn dípò kí ó ní ìmọ́lẹ̀?Tí ó sì ṣókùnkùn dúdú láìsí ìmọ́lẹ̀ kankan níbẹ̀

21. “Mo kórìíra, mo kẹ́gàn àwọn àṣè ẹ̀sìn in yínÈmi kò sì ní inú dídùn sí àpèjọ yín

22. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ mú ọrẹ sísun àti ọrẹ ọkà wáÈmi kò ní tẹ́wọ́n gbà wọ́nBí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ mú àṣàyàn ọrẹ àlàáfíà wá.Èmi kò ní náání wọn.

23. Ẹ gbé ariwo orin yín sẹ́yìnÈmi kò ní fetísí ohun èlò orin yín.

24. Jẹ́ kí òtítọ́ ṣàn bí odòàti òdodo bí ìsun tí kò lé è gbẹ

25. “Àbí ẹ̀yin mú ẹbọ àti ọrẹ tọ̀ mí wání ogójì ọdún ní ihà ìwọ ilé Ísírẹ́lì?

26. Ẹ̀yin ń gbé ibi ìrúbọ àwọn ọba yínibùgbé àwọn òrìṣà yínàní, ti àwọn òrìṣà yín tí ó níyì jùlọ,èyí tí ẹ̀yin fi ọwọ́ ara yín ṣe.

27. Nítorí náà èmi yóò rán an yín lọ sí ìgbèkùn ní ìkọjá Dámásíkù,”ni Olúwa wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ọlọ́run alágbára.

Ka pipe ipin Ámósì 5