Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ámósì 4:8-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Àwọn ènìyàn ń rìn láti ìlú kan sí ibòmíràn fún omiwọn kò rí àrító láti mú,ṣíbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,”ni Olúwa wí.

9. “Lọ́pọ̀ ìgbà ni mo lu ọgbà àti ọgbà àjàrà yínmo fi àrá àti ìrì lù wọ́n.Esú sì jẹ igi ọ̀pọ̀tọ́ àti igi ólífì yín,ṣíbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,”ni Olúwa wí.

10. “Mo rán àjàkálẹ̀-àrùn sí i yínbí mo ti ṣe sí Éjíbítì.Mo fi idà pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín.Pẹ̀lú àwọn ẹṣin tí a kó ní ìgbékùn.Mo kún imú yín fún òórùn ibùdó yín,síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,”ni Olúwa wí.

11. “Mo ti bì ṣubú nínú yín,bí Ọlọ́run ti bi Sódómù àti Gòmórà ṣubúẹ̀yin sì dàbí ògúnná tí a fò yọ kúrò nínú ìjóná,ṣíbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,”ni Olúwa wí.

12. “Nítorí náà, èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí i yín, Ísírẹ́lì,àti nítorí tí èmi ó ṣe èyí sí i yín,ẹ múra láti pàdé Ọlọ́run yín, ẹ̀yin Ísírẹ́lì.”

13. Ẹni tí ó dá àwọn òkètí ó dá afẹ́fẹ́tí ó sì fi èrò rẹ̀ hàn sí ènìyàn,ẹni tí ó yípadà sí òkùnkùntí ó sì tẹ ibi gíga ayé. Olúwa Ọlọ́run Ọ̀gá Ògo ni orúkọ rẹ̀.

Ka pipe ipin Ámósì 4