Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ámósì 2:4-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Èyí ni ohun tí Olúwa wí:“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Júdà,àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padàNítorí wọn ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀wọn kò sì pa àwọn ìlànà rẹ̀ mọ́Nítorí àwọn òrìṣà ti sì wọ́n lọ́nàÒrìṣà tí àwọn Baba ńlá wọn ń tẹ̀lé

5. Èmi yóò rán iná sí orí JúdàÈyí tí yóò jó àwọn ààfin Jérúsálẹ́mù run.”

6. Èyí ni ohun tí Olúwa wí:“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Ísírẹ́lìàní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padàwọ́n ta olódodo fún fàdákààti aláìní fún bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì.

7. Wọ́n fi ẹsẹ̀ tẹ orí àwọn talákà mọ́lẹ̀bí wọ́n ti ń tẹ ẹrùpẹ̀ ilẹ̀tí wọ́n sì fi òtítọ́ du àwọn tí a ni láraBaba àti ọmọ ń wọlé tọ wúndíá kan náàLáti ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́

8. Wọ́n dùbúlẹ̀ lẹ́bá a pẹpẹLórí aṣọ tí wọ́n ti jẹ́jẹ̀ẹ́ní ilé òrìṣà wọnwọ́n sì mu ọtí tí wọ́n san fún ìtanràn.

Ka pipe ipin Ámósì 2