Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ámósì 2:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Èyí ni ohun tí Olúwa wí;“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Móábù,àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà,Nítorí ó ti sun-ún, di eérú,egungun ọba Édómù

2. Èmi yóò rán iná sí orí MóábùÈyí tí yóò jó àwọn ààfin Kéríótì run.Móábù yóò sì kú pẹ̀lú ariwopẹ̀lú igbe àti pẹ̀lú ìró ìpè

3. Èmi yóò ké onídájọ́ rẹ̀ kúròÈmi yóò sì pa gbogbo àwọn ọmọ aládé rẹ́ nínú rẹ̀,”ni Olúwa wí;

4. Èyí ni ohun tí Olúwa wí:“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Júdà,àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padàNítorí wọn ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀wọn kò sì pa àwọn ìlànà rẹ̀ mọ́Nítorí àwọn òrìṣà ti sì wọ́n lọ́nàÒrìṣà tí àwọn Baba ńlá wọn ń tẹ̀lé

5. Èmi yóò rán iná sí orí JúdàÈyí tí yóò jó àwọn ààfin Jérúsálẹ́mù run.”

6. Èyí ni ohun tí Olúwa wí:“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Ísírẹ́lìàní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padàwọ́n ta olódodo fún fàdákààti aláìní fún bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì.

Ka pipe ipin Ámósì 2