Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 9:14-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Nítorí náà ni Olúwa yóò ṣe ké àti orí àti ìrùkúrò ní Ísírẹ́lì,àti Imọ̀-ọ̀pẹ àti koríko-odò ní ọjọ́ kanṣoṣo,

15. Àwọn alàgbà, àti àwọn gbajúmọ̀ ni orí,àwọn wòlíì tí ń kọ́ni ní irọ́ ni ìrù.

16. Àwọn tí ó ń tọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí sì wọ́n lọ́nàÀwọn tí a sì tọ́ ni a ń sin sí ìparun.

17. Nítorí náà, Olúwa kì yóò dunnú sí àwọn ọ̀dọ́mọkùnrintàbí kí ó káàánú àwọn aláìní baba àti opó,nítorí pé gbogbo wọn jẹ́ ìkà àti aláìmọ́ Ọlọ́run,ibi ni ó ti ẹnu wọn jáde.Ṣíbẹ̀, fún gbogbo èyí, ìbínú rẹ̀ kò yí kúròọwọ́ rẹ̀ sì wà ní gbígbéró.

18. Nítòótọ́ ìkà ń jóni bí iná,ó ń jó àtẹ̀wọ̀n, àtẹ̀gùn run,ó sì ń dáná sun ìgbẹ́tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi ń yí lọ sókè ní ọ̀wọ̀n èéfín.

19. Nípaṣẹ̀ ìbínú Olúwa àwọn ọmọ-ogunilẹ̀ náà yóò di gbígbẹàwọn ènìyàn yóò sì di ohun ìdáná,ẹnìkan kì yóò sì dá arákùnrin rẹ̀ sí.

Ka pipe ipin Àìsáyà 9