Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 7:1-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà tí Áhásì ọmọ Jótamù ọmọ Hùṣáyà jẹ́ ọba Júdà, ọba Résínì ti Árámù àti Pẹ́kà ọmọ Rẹ̀málíà ọba Ísírẹ́lì gòkè wá láti bá Jérúsálẹ́mù jà, ṣùgbọ́n wọn kò sì le è borí i rẹ̀.

2. Báyìí, a sọ fún ilé Dáfídì pé, “Árámù mà ti lẹ̀dí àpò pọ̀ mọ́ Éfáímù”; fún ìdí èyí, ọkàn Áhásì àti àwọn ènìyàn rẹ̀ wárìrì gẹ́gẹ́ bí igi oko ṣe ń wárìrì níwájú afẹ́fẹ́.

3. Lẹ́yìn èyí, Olúwa sọ fún Àìṣáyà pé, “Jáde, ìwọ àti ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ Ṣéárì-Jáṣúbù láti pàdé Áhásì ní ìpẹ̀kun ìṣàn-omi ti adágún òkè, ní òpópó ọ̀nà tí ó lọ sí pápá Alágbàfọ̀.

4. Sọ fún un, ‘Ṣọ́ra à rẹ, fi ọkàn balẹ̀, kí o má ṣe bẹ̀rù. Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítoríi kùkùté igi ìdáná méjèèjì yìí, nítorí ìbínú gbígbóná Résínì àti Árámù àti ti ọmọ Rẹ̀málíà.

5. Árámù, Éfáímù àti Rèmálíà ti dìtẹ̀ ìparun rẹ, wọ́n wí pé,

6. “Jẹ́ kí a kọlu Júdà; jẹ́ kí a fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, kí a sì pín in láàrin ara wa, kí a sì fi ọmọ Tábẹ́lì jọba lóríi rẹ̀.”

7. Ṣíbẹ̀ èyí ni ohun tí Olúwa Àwọn ọmọ ogun wí:“ ‘Èyí kò ní wáyéÈyí kò le ṣẹlẹ̀,

8. nítorí Dámásíkù ni orí Árámù,orí Dámásíkù sì ni Résínì.Láàrin ọdún márùnlélọ́gọ́taÉfáímù yóò ti fọ́ tí kì yóò le jẹ́ ènìyàn mọ́.

9. Ṣamaríà ni orí fún Éfáímù,ẹni tí ó sì jẹ́ orí Samaríà náà ni ọmọ Rèmálíà.’ ”

10. Bákan náà Olúwa tún bá Áhásì sọ̀rọ̀,

11. “Béèrè fún ààmì lọ́wọ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, bóyá ní ọ̀gbun tí ó jìn jùlọ tàbí àwọn òkè tí ó ga jùlọ”

12. Ṣùgbọ́n Áhásì sọ pé, “Èmi kì yóò béèrè; Èmi kò ní dán Olúwa wò.”

13. Lẹ́yìn náà Àìṣáyà sọ pé, “Gbọ́ ní ìsinsìnyí, ìwọ ilé Dáfídì, kò ha tọ́ láti tan ènìyàn ní ṣùúrù, o ó ha tan Ọlọ́run ní ṣùúrù bí?

Ka pipe ipin Àìsáyà 7