Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 58:3-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. ‘Èéṣe tí àwa fi ń gbààwẹ̀,’ ni wọ́n wí,‘tí ìwọ kò sì tí ì rí?Èéṣe tí àwa fi rẹra wa sílẹ̀,tí ìwọ kò sì tí ì ṣe àkíyèsí?’“Ṣíbẹ̀ ṣíbẹ̀ ní ọjọ́ ààwẹ̀ yín, ẹ̀yin ń ṣe bí ó ti wù yínẹ sì ń pọ́n àwọn òṣìṣẹ́ yín gbogbo lójú.

4. Ààwẹ̀ yín sì parí nínú ìjà àti asọ̀,àti lílu ọmọnìkejì ẹni pẹ̀lú ẹṣẹ́ ìkà.Ẹ̀yin kò le è gbààwẹ̀ bí ẹ ti ń ṣe lónìíkí ẹ sì retí kí a gbọ́ ohùn un yín ní ibi gíga.

5. Ǹjẹ́ èyí ha ni irú ààwẹ̀ tí mo yàn bí,ọjọ́ kanṣoṣo fún ènìyàn láti rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀?Í haá ṣe kí ènìyàn tẹ orí i rẹ̀ ba bí i koríko láṣán ni bíàti ṣíṣùn nínú aṣọ ọ̀fọ̀ àti eérú?Ṣé ohun tí ẹ̀ ń pè ní ààwẹ̀ nìyí,ọjọ́ ìtẹ́wọ́gbà fún Olúwa?

6. “Ǹjẹ́ irú ààwẹ̀ tí mo ti yàn kọ́ ni èyí:láti já gbogbo ẹ̀wọ̀n àìsòdodoàti láti tú gbogbo okùn àjàgà,láti tú gbogbo àwọn ti à ń ni lára sílẹ̀àti láti fọ́ gbogbo àjàgà?

7. Kì í ha á ṣe láti pín oúnjẹ yín fún àwọn tí ebi ń paàti láti pèsè ibùgbé fún àwọn òtòsì tí ń rìn káàkirinígbà tí ẹ bá rí ẹni tí ó wà níhòòhò, láti daṣọ bò ó,àti láti má ṣe lé àwọn ẹ̀jẹ̀ àti ẹran yín sẹ́yìn?

8. Nígbà náà ni ìmọ́lẹ̀ rẹ yóò tàn jáde bí òwúrọ̀àti ìmúláradá rẹ yóò farahàn kíákíá;nígbà náà ni òdodo rẹ yóò sì lọ níwájúù rẹ,ògo Olúwa yóò sì jẹ́ ààbò lẹ́yìn rẹ.

Ka pipe ipin Àìsáyà 58