Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 55:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. “Ẹ wá, gbogbo ẹ̀yin tí òrùngbẹ ń gbẹ,ẹ wá sí ibi omi;àti ẹ̀yin tí kò ní owó;ẹ wá, ẹ rà kí ẹ sì jẹ!Ẹ wá ra wáìnì àti mílíìkìláìsí owó àti láìdíyelé.

2. Èéṣe tí ẹ fi ń ná owó fún èyí tí kì í ṣe àkàrààti làálàá yín lórí ohun tí kì í tẹ́nilọ́rùn?Tẹ́tísílẹ̀, tẹ́tí sí mi, kí ẹ sì jẹ èyí tí ó dára,bẹ́ẹ̀ ni ọkàn yín yóò láyọ̀ nínú ọrọ̀ tí ó bójúmu.

3. Tẹ́tí sílẹ̀ kí o sì wá sọ́dọ̀ migbọ́ tèmi, kí ọkàn rẹ lè wà láàyè.Èmi yóò dá májẹ̀mú ayérayé pẹ̀lúù rẹ,ìfẹ́ Òtítọ́ tí mo ṣèlérí fún Dáfídì.

4. Kíyèsí i, mo ti fi òun ṣe ẹlẹ́rìí fún àwọn ènìyàn,olórí àti apàṣẹ fún àwọn ènìyàn.

Ka pipe ipin Àìsáyà 55